Tuesday 22 August 2017

Ìkéde tí Ààrẹ Muhammad Buhari ṣe

Èyí ni ìkéde tí Ààrẹ Muhammad Buhari ṣe ní ọjọ́ kọkànlélógún, oṣù kẹjọ ọdún 2017 (21/08/2017).

Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà,

1) Mo dúpẹ́ fún Ọlọ́run àti gbogbo ọmọ orílè Nàìjíríà fún àdúrà yín, inú mi dùn láti padà sí orílè èdè Nàìjíríà tí mo tí jẹ Ààrẹ.

2) Dídúró mi ní orílè-èdè United Kingdom, gbogbo ohun tí ó ń lọ ní orílè èdè Nàìjíríà ni mo mọ. Àwọn ọmọ orílè èdè Nàìjíríà gbójú gbóyà láti sọ ohunkóhun, ṣùgbọ́n inú mi bàjé láti gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ mìíràn tí wọ́n ń sọ, pàápàá jù lọ lórí ẹ̀rọ ayélujára.

3) Ní ọdún 2003 lẹ́yìn ìgbátí mọ darapọ̀ mọ òṣèlú, Olóògbé olóyè Emeka Ojukwu wá sí ìlú mi ní Daura gẹ́gẹ́bí àlejò. A sọ̀rọ̀ ni kíkún nípa awon ìpèníjà tí orílè èdè Nàìjíríà ń dójú kọ fún ọjọ́ méjì tí Ilé sii sú báwa níbè. Àwa méjèèjì fi orí ọ̀rọ̀ wa kò wípé orílè èdè Nàìjíríà gbọdọ̀ wà ní Ìsòkan.

4) Ìsòkan orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ti ní ìyanjú kò sì ní ìdúnàdúrà nínú. Àko ní fi ààyè gba àwọn alaimokan láti dá wàhálà àti rògbòdìyàn sílè nítorí bí nkan bá bàjẹ́ tán, ńṣe ni wọn yíò sálọ tí wọn yíò sì jẹ́ kí ẹ̀jẹ̀ alaise ṣòfò.

5) Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó ní aàǹfààní láti gbé ayé àti láti lépa ohun rere tí wọ́n bá fẹ́ ṣe ni ibikíbi ni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láìsí ẹnì kankan tí yíò di wọn lọ́wọ́.


6) Mo nígbàgbọ́ wípé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó fi ara mọ́ èróngbà yìí.

 7) Eléyìí kìí ṣe láti di àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti má mọ ohun tí ó kàn wón. Ṣùgbọ́n ẹwà àti ifamora orílẹ̀ èdè gbọdọ̀ fi àyè gba onírúurú ẹgbẹ́ láti ṣisẹ́ kí orílè èdè yìí le tẹsiwaju.

8) Àwọn ilé ìgbìmò Asòfin àti ilé ìgbìmò ní àwọn ìlú kọ̀ọ̀kan ni ẹ̀tọ́ láti  gbìmọ̀ àti láti ṣe ìwádìí tí ó dára.

9) Ìlàkàkà àwọn ọmọ ilẹ̀ ìgbìmò náà ni wípé ó dára kí gbogbo wa máa gbé papọ ni ìrépọ̀ kí ó má sí ìpínyà láàrin wa.

10) Mo ń gbìyànjú láti má jẹ́ kí ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn bá  àwọn elétò ààbọ̀ látàrí àṣeyọrí tí wọ́n tí ṣe ni ọdún kan àti oṣù díè sẹ́yìn.

11) Wọ́n gbọdọ̀ lé Ìgbé sùnmọ̀mí àti ìwà ọ̀daràn jìnà kí ó le fún gbogbo wa ni àǹfààní láti gbé ní ayọ̀ àti àlàáfíà.

12) Fún ìdí yìí a gbọdọ̀ tún ṣòkòtò wa ṣán làti gbé ogun tí àwọn wọ̀nyí:

Agbé sùmòmí Boko Haram
Àwọn gbọmọgbọmọ, àwọn Darandaran àti àgbẹ̀ àti
Èdè àiyedè láàrin wa pẹ̀lú iranlọwọ àwọn olóṣèlú. A gbọdọ̀ dojú kọ wón.


13) Gbogbo olólùfẹ́ orílè èdè Nàìjíríà, ìsisẹ́ papọ wa yíò jẹ́ kí á le gbé ogun tí àwọn ìpèníjà wọ̀nyí:

·   Ètò ọrọ̀ ajẹ́

·     Ìdàgbàsókè ètò òṣèlú àwa araawa
·       Àti àlàáfíà tó yè kooro láàrin gbogbo ọmọ Nàìjíríà

14) Máa rí wípé gbogbo àwọn ìpèníjà yìí ni a borí wọn. Inú mi dùn láti padà sí orílè-èdè Nàìjíríà.

15) Ẹsẹ́ púpọ̀, Èdùmàrè a tún orílè èdè Nàìjíríà ṣe.

Àmín.

#EdeYorubaRewa