Monday 29 May 2017

Ayẹyẹ ìjọba tiwantiwa

Ó pé ọdún kejìdínlógún tí orílè èdè Nàìjíríà tí ń lo ìjọba tiwantiwa leyin igba ti ológun tí ń darí wá.

Mo kí gbogbo àwọn ọmọ orílè èdè Nàìjíríà nílé lóko àti lẹ́yìn odi wípé a kú ayẹyẹ ìjọba tiwantiwa (Happy Democracy day). Mo mọ wípé inú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni o dùn látàrí bí nkan ṣe rí, ẹ jẹ́ kí a nígbàgbọ́ ni àwọn tí ó wà lórí ipò báyìí wípé wọn a mú wa dé èbúté ògo.

"Ọ̀rọ̀ Yorùbá kan ló sọ wípé sùúrù kìí pọ̀ jù àfi tí kò bá ní tó."
Mo mọ wípé ìjọba tí a ní lori ipò báyìí ń gbìyànjú láti jẹ́ kí orílè èdè Nàìjíríà dara,ki o rọrùn fún tolórí telémù,Ǹkan tí ó ti bá jẹ́ fún ọdún mẹ́tadínlógún kólé ṣe ẹ túnṣe láàrin ọdún díè tí àwọn ìjọba yìí dé ibè ìdí nì tí ó fi ye ká ní sùúrù.
Ìjọba  Nàìjíríà,  ẹ bá wà tún orílè èdè wa ṣe, ẹsẹ àtúnṣe sì gbogbo ohun tí oti bàjé kí inú àwọn tí ó dibo fún yín lé dùn.

Iṣẹ́ wa lọ́wọ́ àwa náà tí a jẹ́ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà, lábé bí ó ti wù kí ó rí Ẹjẹ́ kí àwa náà rán ìjọba lọ́wọ́ látàrí kí a jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn rere

Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ẹ jẹ ká ní sùúrù àti èmi ìfaradà fún Ààrẹ Muhammad Buhari àti gbogbo àwọn tí ó kó sódì kí wọn lè mú wa dé èbúté ògo.

Dídára orílè èdè Nàìjíríà ó wà lọ́wọ́ èmi àti ìwọ ẹ jẹ́ kí á jọ ṣe.orílẹ̀ èdè Nàìjíríà yíò dára tí ó bá dára tán kí wọn má fi wa ṣe àwátì

🇳🇬🇳🇬🇳🇬🇳🇬🇳🇬
Semiat Olufunke Tiamiyu
#EdeYorubaRewa



Thursday 25 May 2017

Ìtàn òwe Yorùbá

Ìtàn tí ó rò mó òwe Yorùbá yìí,

                   "Kí lo rí l'ọ́bẹ̀ tí fi waaro ọwọ́."

Ní bí ọdún díè sẹ́yìn, ìlú kan wà tí wọ́n ń pè ní Kuo, ó wá ní Bode Saadu ni Ìpínlẹ̀ Kwara ṣùgbọ́n ìlú tí à ń sọ yìí jóná ni ọdún 1814.

Gbogbo Yorùbá kó ló máa ń lo òwe yìí tẹ́lẹ̀, ogun ni ó sì fà á tí òwe yìí fi wáyé.
Ìlú tí a ń pè ní Kuo yìí ni olórí tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Sholá Gberú. Nígbà tí ìlú Kuo jóná Sholá Gberú kò gbogbo àwọn ọmọ, ẹrú àti gbogbo ohun tí wọ́n ni lọ sí ìlú Ilorin,nígbà náà afonja wa láyé. Ìlú kan wà láàrin Ọ̀yọ́ àti Ilorin,ìlú Gbógun ni ìlú náà ń jẹ́, tí ogún bá sì fẹ́ ja Ọ̀yọ́ wọn gbodo kọ́kọ́ ja ìlú Gbógun tí à ń Wiyi. Nígbà tí wọ́n fẹ́ kogun ja ìlú Gbógun ALÁNÀMÚ ni lèdí àpò pọ̀  láti kogun ja ìlú Gbógun.


Arákùnrin tí wọ́n ń pè Alánàmú Pankere ní o ma ń fi jà, tí ó bá ti fi náà ẹni tí wọ́n dìjọ ń jà fi ń jà, ẹni náà ara rẹ̀ yíò wálè yíò sì na'wọ́ mú ẹni náà ìdí rẹ tí wọ́n fi ń pe ni ALÁNÀMÚ.
Alánàmú sì so ọwọ́ pò mo Ilorin, wọn sì mú orí ìyàwó ọ̀pẹ̀lẹ̀ mó ara, Wọ́n fún ní májẹ̀lé pé kí ó fi si inú oúnjẹ. Wọ́n rán àgbà ọmọ Sholá Gberú sí ọ̀pẹ̀lẹ̀, ìyàwó ọ̀pẹ̀lẹ̀ dáná oúnjẹ, ó sì ti fi májẹ̀lé si inú ounje náà, ọ̀pẹ̀lẹ̀ àti ọmọ Sholá Gberú tí fọ ọwọ́, bí ọmọ Sholá Gberú tí bu òkèlè pé kí ohun fi kan ọbẹ̀
Ó bá wararo ọwọ́. Ọ̀pẹ̀lẹ̀ bíi pé kí lórí l'ọ́bẹ̀ tí ó fi wararo ọwọ́, ló bá ní májẹ̀lé rẹ nínú ọbẹ̀.....
Báyìí ni Ọ̀pẹ̀lẹ̀ ni Bí kú ilé ọ bá pani tode ó lè pani.

Ìtàn tí ó rò mó òwe KÍ LO RÍ L'Ọ́BẸ̀ TÍ Ó FI WAARO ỌWỌ́. májẹ̀lé ni ó rí l'ọ́bẹ̀ tí ó fi Wararo ọwọ́.

Mo lérò wípé ẹ gbádùn ìtàn yìí.

#EdeYorubaRewa


Sunday 14 May 2017

Ìtàn ránpé.




E bá Ẹfọ̀n l'ábàtà, ẹ yọ Ọ̀bẹ tí, Omi le rò wípé ó mu kú ni?

Ìtùmò Òwe yìí: a kìí kánjú tàbí yára sí àwọn aàǹfààní tí a bá rí nítorí ó lè jẹ́ iṣẹ́ takuntakun tí ẹnìkan tí ṣe.

Ìtàn ránpé tí ó rò mó Òwe yìí.

Ní ayé àtijó bàbá ọdẹ kan wà, bàbá yìí tí ń de ìgbẹ́ fún ọ̀sẹ̀ díè ṣùgbọ́n kò rí ẹran kankan pa. Nígbà tí ó ṣe èdùmàrè jẹ́ kí ó rí ẹran Ẹ̀fọ̀n, ó yin Ẹfọ̀n yìí ni Ìbon ṣùgbọ́n ìbon yìí kò pá Ẹfọ̀n yìí kíákíá leyi tí ó mú kí Ẹfọ̀n yìí sálọ. Bàbá ọdẹ yìí ri ó sì rántí pé ohun kò ní ohun jíjẹ fún ọjọ́ díè sẹ́yìn, èyí sì mu kí bàbá ọdẹ yìí wá Ẹfọ̀n pẹ̀lú ìgbàgbọ́ pé ìbọn tí ó bá ó ti pá. Lẹ́yìn ọjọ́ díè, Ẹfọ̀n yìí kú sí àgbàlá ẹnikẹ́ni nínú abúlé, kí bàbá ọdẹ yìí tó dé ibè àwọn ènìyàn abúlé náà tí rí wípé Ẹfọ̀n tí kú sí inú àgbàlá wọn leyi tí wọ́n rò wípé òrìṣà àti Baba ńlá àwọn ni ó see

Gbogbo ènìyàn sì lọ sí ibi tí Ẹfọ̀n yìí kú sí pẹ̀lú Ọ̀bẹ láti pín láàrin ara wọn, ṣùgbọ́n kí wọ́n tó bẹrẹ si maa ge bàbá Ọdẹ yìí dé ibè ó sì dá wọn dúró ní o bá sọ wípé "E bá Ẹfọ̀n l'ábàtà, ẹ yọ Ọ̀bẹ tí, Omi le rò wípé ó mu kú ni?"

Mo lérò wípé ìtàn ránpé yìí ni ìtumò sí yín.
Ẹsẹ́ púpọ̀
Ẹ kú ojú lọ́nà fún tí ọjọ́ méjo..
#EdeYorubaRewa

Tuesday 9 May 2017

Òrùn Ati Òṣùpá

Ìtàn Òrùn Ati Òṣùpá fún àkà gbádùn yín......
nígbà ìwásẹ̀, ọba ọdẹ Ọ̀run níse alákoso ohun gbogbo, ìkáwọ́ rẹ̀ ṣì ni gbogbo ohun tí a dá wà.ọba ọdẹ Ọ̀run ní ìyàwó , ósì tún bí ọmọ méjì. ÒRÙN àti ÒSÙPÁ ni ọmọ méjì tí ọba ode ọ̀run bí. Òrùn àti òsùpá fẹ́ràn ara wọn gidigidi, tí ó jẹ́ wípé bí òsùpá ò bá ṣí nílé òrùn kòní jẹun àfi ìgbà tí òsùpá bá dé ,bẹ́ẹ̀ nọ sì ni òsùpá bí òrùn kò bá dé kò ní jẹun.
Ní ọjọ́ kan ọba ọdẹ ọ̀run ránsé sí òṣùpá àti òrùn ọmọ rẹ wìpè kí wọn wà rí òhun. nígbàti wọn dé bè , ọba ọdẹ ọ̀run sọ fún wọn wípé òhun fẹ rìn irìnàjò kan tí yóò sì pẹ́ kí òhun tó padà , óní kí òṣùpá àti òrùn lọ fi oríkorí kí wọn se àpérò ẹni tí yóò delé de òhun tí òhun bá wà ní ìrìnàjò. Wọ́n dúpé lọ́wọ́ bàbá wọn, wọn sì se ìlérí láti se gẹ́gẹ́ bí bàbá wọn ti sọ.
Ní ọjọ́'rù ọ̀sẹ̀ kan náà, òṣùpá àti òrùn fi ojú kan ra, sùgbón ọ̀rọ̀ ò wọ̀ láàrín àwọn méjèèjì lérí ẹni tí yóò délé nígbàtí bàbá wọn bá lọ. òṣùpá ní òhun ọkọ ẹgbàágbèje ìràwọ̀ ni yóò delé de bàbá àwọn, béèni òrùn tutọ́ sókè fojúgbàá wípé òhun ìmólè ọmọ aráyé ni yóò delé de bàbá àwọn , óní láì sí èmi òrùn inú òkùnkùn biribiri ni ayé kò bá wà,ó ní èmi àfi ojojúmó dára bí egbin, òsùpá sọ wípé tí o bá rí béè ọmọ aráyé òní máà sọ wípé isẹ́ lò òsùpá se lájùlé òrùn, óní òhun ni yóò delé de bàbá wọn.
Bí wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀ náà bí ẹni gba igbá ọtí re ,títí ó fi di ìjà. òsùpá lu òrùn ní ìlú ẹni lu bàrà, òrùn náà sí lu òsùpá bákan náà.
nígbátì bàbá wọn gbọ́ sí ọ̀rọ̀ náà inú rẹ bàjé,óní kí wọ́n pe àwọn méjèèji wá sí àgbàlà olódùmarè,ní ibẹ̀ ló ti jẹ kóyé wọn wípé òhun ọba ọdẹ ọ̀run ní se alákòso ọ̀sán àti òru,óní ní ìdí èyí òhun yóò pin ìlú náà sí méjì,óní kí òṣùpá máà jọba lérí òru , ósì ní kí òrùn máà jọba lóri ọ̀sán wọn kò sì gbọdọ̀ fi ojú kan ra gẹ́gẹ́ bí ìjìyà ẹ̀sẹ̀ wọn.
Ní ọjọ́ yíí inú òṣùpá àti òrùn bàjẹ́ nítorí wọn kòní fo jú kan ra mọ́ àti wípé àyè àti má se bí ẹbí ti dópin. Ìgbà kúgbá tí òrùn àbí òṣùpá báti rántí ìdájó yii ,nínú ọdún wọn a máa sunkún lọ́pọ̀lọpọ̀ ,ekún wọ̀nyí ni àwa ọmọ ènìyàn ńpè ní ÒJÒ.
#Ìbéèrè
Kíni Èkó Inú Ìtàn Yìí?
#EdeYorubaRewa




Ọ̀RỌ̀ ÌDÚPẸ́

Kíni mo jẹ́? Tani ni mí? Tí Kò bá sí èyin, kò lè sí ojú ìwé #EdeYorubaRewa. Yorùbá bò wọn ní "Àgbáj'ọwọ́ la fi ń sọ̀'yà, Àjèjí ọwọ́ kan kò gbẹ́'rù dó'rí" leyi tí ó túmọ̀ sí wípé ọlá Ọlọ́run àti ọlá gbogbo olólùfẹ́ Èdè Yorùbá Rẹwà ni ó fún mi ní agbára láti máa ṣe ohun kékeré tí mò ń ṣe láti gbé èdè Yorùbá lárugẹ.... Mọ wá dúpẹ́ púpọ̀ lọ́wọ́ gbogbo àwọn tí wọ́n fẹ́ràn àti àwọn tí wọ́n tẹ́lẹ̀ wa lórí ẹ̀rọ ayélujára Facebook, Twitter, Instagram, Blog àti WhatsApp,èdùmàrè ò ní paná ìfẹ́ wá.
Mo sì tún fi àsìkò yìí dúpẹ́ lọwọ gbogbo àwọn tí wọ́n ni ìgbẹ́kẹ̀lé dáadáa nínú wa ti wọ́n sì fi ìfẹ́ báwa ra aṣọ tí a ṣe láti fi ṣe ayẹyẹ ọdún kan, elédùmarè a nífẹ̀ẹ́ gbogbo yín ooo.
Mo wá ro gbogbo àwọn tí wọ́n ra aṣọ náà kì wọn ó fi àwòrán wọn ránṣé sí mi láti lè fi sì ojú ìwé EdeYorubaRewa
Ẹsẹ́ púpọ̀
#EdeYorubaRewa