Tuesday 27 February 2018

ÌDÚPẸ́

Kíni mo jẹ́?
Tani ni mí?
Tí Kò bá sí èyin, kò lè sí ojú ìwé #EdeYorubaRewa. Yorùbá bò wọn ní "Àgbáj'ọwọ́ la fi ń sọ̀'yà, Àjèjí ọwọ́ kan kò gbẹ́'rù dó'rí" Yorùbá tún sọ wípé "ọ̀pọ̀ èèyàn ní jẹ́ janmọ ẹnìkan kìí jẹ́ àwa de"leyi tí ó túmọ̀ sí wípé ọlá Ọlọ́run àti ọlá gbogbo olólùfẹ́ Èdè Yorùbá Rẹwà ni ó fún mi ní agbára láti máa ṣe ohun kékeré tí mò ń ṣe láti gbé èdè Yorùbá lárugẹ.... Mọ wá dúpẹ́ púpọ̀ lọ́wọ́ gbogbo àwọn tí wọ́n fẹ́ràn ojú ìwé #ÈdèYorùbáRewà àti àwọn tí wọ́n tẹ́lẹ̀ wa lórí ẹ̀rọ ayélujára Facebook, Twitter, Instagram, Blog àti WhatsApp,èdùmàrè ò ní paná ìfẹ́ wá.

Ẹ dákún mo rọ gbogbo òbí láti jé kí a fi èdè Yorùbá kó àwọn ọmọ wa láti lè gbé èdè wa lárugẹ, torí mò ń gbọ́ wípé èdè Yorùbá ò ní pé kú àti wípé wón ní àwọn òyìnbó aláwò funfun yíò máa kọ́ wa ni èdè wa leyi tí kò gbọdọ̀ ṣẹlẹ̀, ai mó wá ní ṣẹlẹ̀ rẹ̀ ó wà ní ọwọ́ ÈMI àti ÌWỌ.

Ní tèmi ń ò ní fi ọwọ́ òsì júwe ilé bàbá mi, ìwọ ńkọ́?
Ẹsẹ́ púpọ̀

Www.edeyorubarewa.com
Www.facebook.com/edeyorubarewa

#EdeYorubaRewa

Sunday 7 January 2018

Ìtàn Alarinrin apá kejì

ỌBA LÓ LADE. ÌJÒYÈ NÁÀ LÓ NI ILEKE. ITAN NTE SÍWÁJÚ.
ÀKỌLÉ ITAN: ṢỌ ẸRÚ KO

APÁ KEJÌ

Ibẹru bojo tí bàa gbogbo ara ilu ẹlẹgan, ṣe ogún ó dàbí ẹni ń jiyan, bẹ́ẹ̀ ni ó dàbí ẹni ń jẹka.
Are ni ajanimogun nilu ẹlẹgan,ọdẹ ni àmọ́ ọdẹ tí rẹ kì npa ẹkùn bẹ́ẹ̀ ni kí npa àgbọ̀nrín. Ọdẹ etile ló ńṣe bí kò pá Ọya, kò pá emo, kò sì de isa okete. Nígbà tó kú ọjọ marun kí àsìkò tí ìlú tẹrẹ dá fún ìlú ẹlẹgan pé, ajanimogun gbéra lọ bá àwọn ilumoye pé tí wọ́n bá lè gbà òun láyé, òun ṣetan láti lewaju ogún fún wọn, ó sì dájú pé ajaye ni òun yóò jagun náà.
Tika tẹgbìn ni àwọn olóyè wo ajanimogun, wọn ní bóyá ni nkan ó ti tà sì lọpọlọ. Abi báwo ni ọdẹ tí npa ẹmọ, Pa afé ṣe fẹ lọ koju ogún, oogun wo loni tí yóò fi jagun ọhun ni ajaye? Àbí torí kí ajanimogun lè d'oba ló ṣe ni òun fẹ lọ dojú kọ ogún?? Gbogbo ìbéèrè yìí ni àwọn olóyè nro lọ́kàn ara wọn,àmọ́ kò ye wọn.
Wọn ní kí ajanimogun sì máa lọ náà pé tí yóò bá fi di ọjọ́ kejì, àwọn yóò ti mọ̀ ibi tí àwọn yóò bá ìyára ja lórí ọrọ náà.
Lẹ́yìn tí ajanimogun kúrò lọdọ àwọn olóyè, iyalode ni kí wọ́n jẹ́ káwọn gba ajanimogun láàyè láti lọ jagun, bóyá eledua lè gbé ògo fún ọlẹ rẹ. To bá sì ṣe bẹ́ẹ̀ bá ogún lọ, a jẹ pe ohun ojú nwa lójú nri. Àwọn olóyè tó kú fara mọ èrò iyalode, wọn si pinnu láti tẹle aba rẹ.
Ní òwúrọ ọjọ kejì àwọn olóyè rán onise sì ajanimogun pé ìlú tí fara mọ èrò rẹ, wọn si ti gba pe ko lọ dojú kọ ogún fún wọn. Wọn súre fún pé yóò lọ rẹ, yóò sì bo rè. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún fi ikilọ ati àdéhùn tí ọ̀rọ̀ wọ́n lẹ́yìn. Wọn ní bí ajanimogun bá kọ láti ṣẹ́gun pípa ni ilu yóò pá òun àti gbogbo ẹbi rẹ run,àmọ́ bí ó bá lè já ogún náà ni ajaye, àwọn yóò fi jọba ìlú ẹlẹgan tuntun.....
ṢE AJANIMOGUN YÓÒ ṢÍ LỌ SOJU OGUN PẸ̀LÚ ALAKALE TI ÌLÚ GBÉ SI NÍWÁJÚ BÁYÌÍ????
ITAN Ń TẸ ṢÍWÁJÚ

Ẹ fojú sọ́nà fún apá kẹta




Láti ọwọ́ Ọ̀gbẹ́ni Aremo Jah-Akewi


www.facebook.com/EdeYorubaRewa

#EdeYorubaRewa

Thursday 4 January 2018

Àkọlé ìtàn : ṢO ẸRÚ KO

ÀTI SE ÈÉ, Ó TI JINÀ.
Àkọlé ìtàn : ṢO ẸRÚ KO

APÁ KÌÍNÍ

Ojúmọ́ tí n mo, ooye tí bẹ̀rẹ̀ si ni là, ó ti ń bọ̀ sọ wo afemoju. Àwọn aráàlú elegan tí ń gbéra nílé láti gba ẹnu ìṣe wọn lọ, ṣe ìdí isẹ ẹni là tí ń mọni lole.
Bi àwọn èèyàn ti ń jí ni wọn bẹ̀rẹ̀ si ni gbo tí kowe nke labaadi. Bí ojúmọ́ ṣe ń mọ sì bẹẹ nígbè ẹyẹ yìí túbọ̀ n pọ sì. Ara bẹ̀rẹ̀ si fú àwọn aráàlú ohun lè mú kí kowe máa ké lafemoju. Se kowe ó kúkú nke lásán, ó ní láti jẹ pe ohun burúkú kan tí ṣẹlẹ̀ sí lu elegan ni.
Nígbà tí yóò fi di ÒWÚRỌ̀ kukutu, ní alago ọba bẹ̀rẹ̀ si ni lu aago, kaluku ń jáde wá gbọ ìṣe tí alaago náà fẹ jẹ́. Òfò ńlá tí ṣe ìlú elegan, àkùkọ tí kò lẹyin ọmọkùnrin alágbára. Alago jabo fún gbogbo ìlú pé kabiyesi àwọn, tí ńṣe ọba ọlọbẹ tí ìlú ẹlẹ́gan tí waja lóru mójú. Tori náà isede yóò wà fún odindi ọjọ méje láti ṣe oro fún ìsìnkú ọba. Gbogbo ìlú kan gogo nítorí ìròyìn láabi tí wọn gbo.
Àwọn ilumoye ṣeto bí wọn yóò ṣe fi ilẹ bo àṣírí òkú ọba, bí irun ti ń bo àṣírí orí.
Àdánù ńlá gbaa ni ikú ọba ọlọbẹ jẹ́ fún gbogbo ìlú ẹlẹ́gan pátápátá. Ìgbà ìṣàkóso rẹ tú t'onile t'alejo lára, eku nke bí eku, ẹyẹ nke bí ẹyẹ bẹẹ lọmọ ènìyàn ń fohùn bí èèyàn, amo ikú ṣe ká bo se fi ọba ọlọbẹ là gbogbo ìlú ẹlẹ́gan lójú.
Lẹyin oṣù kan tí ọba ọlọbẹ tí waja ni ilu tẹrẹ ranse ogún sì wọn, ṣe fami nfa ọ kúkú ti wá laarin ọba ìlú tẹrẹ yìí pẹlu ọba ọlọbẹ kò tó di pé ó waja. Èrò àwọn ilumoye tẹ́lẹ̀ ni pé bóyá ìlú tẹrẹ yóò jáwọ lórí ọ̀rọ̀ náà nígbà tí ọba ọlọbẹ tí waja, àmọ́ ibi tí wọ́n fojú sì ọ̀nà ó gbà ìbè, ó jọ bí ẹni pé ọrọ ti fẹ́ bá ẹyin yọ.
Ọ̀sẹ̀ mẹta péré ni ilu tẹrẹ fún ìlú ẹlẹ́gan láti lọ múra ogún silẹ, torí ìjà nbo kànnàkànnà ṣe tàn tó fẹ́ bo ẹyẹ ẹga. Àwọn ilumoye ṣètò pé kí àwọn ìdílé tó njẹ ọba fà ọmọ oyè silẹ, kí wọn lé yàn ọba èyí tí yóò lewaju ogún tó nbo lọ́nà. Àmọ́ kò sẹni tó yọjú.
Ọ̀pọ̀ lo wù kó joyè, àmọ́ aile fara ẹni jin ó jẹ ki ẹnikẹ́ni yọjú láti gorí apere bàbà rẹ. Mo ńbọ

ìtàn wá láti ọ̀dọ̀ Ọ̀gbẹ́ni Aremo Jah-Akewi

Ẹ fojú sọ́nà fún apá kejì.

www.facebook.com/EdeYorubaRewa

#EdeYorubaRewa