Thursday 14 September 2017

Ìjàpá àti ẹyẹ Àdàbà

Èyí ni Àlọ́ àpagbè fún gbogbo olólùfẹ́ ojú ìwé yìí, mọ lérò wípé ẹ ò gbádùn ẹ.

Àlọ́ oooo
Àlọ́ ọọọọ
Àlọ́ yìí dá lórí #ÌjàpáatiẹyẹÀdàbà

Gégé Bí ẹ̀yin náà ti mọ̀, alàgàbàgebè ni Ìjàpá, olè àti ọ̀kánjúwà ni pẹ̀lú. Ní ayé àtijó, Ìjàpá àti Ẹyẹ Àdàbà jọ ń ṣe ọ̀rẹ́. Àdàbà ni ẹṣin kan tí ó máa ń gùn kiri tí Ìjàpá kò sì ní nǹkankan. Ìjàpá ronú lọ́jọ́ kan, ó sì gbèrò bí yóò ti ṣe pa ẹṣin Àdàbà. Ó rí pé Àdàbà gbayì láàrin àwùjọ èyí tí kò dùn mọ̀ Ìjàpá nínú.

Nígbà tí ó di ọjọ́ kan Ìjàpá dá ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yín, ó pa ẹṣin Àdàbà. Àdàbà kò bínú sí kíkú tí ẹṣin rẹ̀ kú. Ohun tí ó ṣe ni pé ó gé orí ẹṣin náà ó bòó mọ́lẹ̀ ó wá fi ojú ẹṣin si ìta tí ènìyàn leè máa rí dáadáa. Bí Ìjàpá ti ń kọjá lọ ni ó rí ojú tí ó yọ síta. Eléyìí yàá lẹ́nu, kíá ó gbéra ó di ilé ọba. Nígbà tí ó dé ààfin, ó sọ fún ọba pé òun ti rí ibi tí ilé gbé lójú. Eléyìí ya ọba lẹ́nu, ó sì tún bí Ìjàpá bóyá ohun tí ó ń sọ dáa lójú. Ìjàpá sọ fún ọba pé ó dá òun lójú, ó sì tún wá fi dá ọba lójú pé bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ kí ọba pa òun. Nígbà yìí ni ọba pe gbogbo àwọn ìjòyè àti ẹmẹ̀wà rẹ̀ pé kí àwọn lọ wo ibi tí ilẹ̀ gbé lójú. Ìjàpá ni ó síwájú tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ orin báyìí pé;

Ìjàpá___________ Mo ti rí ibi ilẹ̀ gbé lójú
Agberin________ Ilẹ̀
Ìjàpá___________ Mo ti rí ibi ilẹ̀ gbé lójú
Agberin________ Ilẹ̀

Báyìí ni gbogbo wọn ń dá reirei lọ sí ibi tí ilẹ̀ gbé lójú. Bí Àdàbà ti gbọ́ ohun tí Ìjàpá ṣe yìí ni ó bá sáré lọ sí ibi tí ó bo orí ẹṣin rẹ̀ tí ó wó sí, ni ó bá wú orí náà kúrò lọ sí ibòmíràn. Nígbà tí ọba ìjòyè àti àwọn ẹmẹ̀wà dé ibi tí Ìjàpá wí, wọn kò rí nǹkan kan Ìjàpá bẹ̀rẹ̀ sí tú ilẹ̀ kiri títí kò rí ojú kankan. Ìgbà yí ni ọba bínú gidigidi pé Ìjàpá pa irú irọ́ tí ó tó báyìí àti pé ó tún da òun, àwọn ìjòyè àti àwọn ẹmẹ̀wà láàmú láti wá wo ohun tí kò sí níbẹ̀. Kíá ni ọba pàṣẹ pé kí wọn ó ti ojú Ìjàpá yọ'dà kí wọn ó ṣì ti ẹ̀yìn rẹ̀ kì í bọ àkọ̀.Eléyìí jásí pé wọn paá. Báyìí ni Ìjàpá fi ìlara pa ara rẹ̀.

#EdeYorubaRewa

Àlọ́ àpagbè

Àlọ́ àpagbè míràn fún gbogbo olólùfẹ́ ojú ìwé yìí. Mo lérò wípé ẹ ò gbàdúrà e
Àlọ́ oooo
Àlọ́ ọọọọ
Àlọ́ yìí dá lórí #ẸkùnàtiIkùn

Ní ìlú àwọn ẹranko, kìnnìún ni Ọba wọn. Nígbà tí ó di ọjọ́ kan, Ọba ẹranko pe gbogbo àwọn ẹranko jọ, ó sọ fún wọn pé òun fẹ́ dá ọjọ́ tí àwọn ẹranko yóò wa ṣe eré fún òun. Ó sọ pé ẹni tí ó bá lu ìlù dáadáa òun yóò da lọ́lá. Nítorí ìdí èyí ó ní kí ẹranko kọ̀ọ̀kan lọ kan ìlù. Gbogbo àwọn ẹranko gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọba, wọ́n dárí lọ sí ilé wọn. Ẹni kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ẹranko ń gbìyànjú à ti kan ìlù. Ṣùgbọ́n dípò kí ẹranko kan tí orúkọ rẹ ń jẹ ikún ó kan ìlù tie, ní ṣe ni ó lọ gbé ìlú ẹkùn níbi tí ẹkùn gbé e sí. Ẹkùn bẹ̀rẹ̀ sí wa ìlú rẹ, ó wàá títí kò ri. Nígbà tí ó di ọjọ́ aré, ẹkùn jí ni kùtùkùtù ó lọ dúró ní ọ̀nà tí ó lọ sí ilé kìnnìún ọba ẹranko. Bí ẹranko kọ̀ọ̀kan bá ti fe kọjá ni ẹkún yóò yọ sí i tí yóò sì sọ pé kí ó lu ìlù rẹ̀ kí òun gbọ́. Orin ni ẹkún fi ń sọ eléyìí fún wọn tí orin náà sì lọ báyìí :

Ẹkùn________ Ríkíríkijàn
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ríkíríkijàn
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ aré
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ ayò
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Wọ́n ní á kànlù, mo kànlù
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Mo gbé ìlú mi s'àgbàlá
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọmọ ẹranko gbé e lọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Lùlù rẹ kí n gbọ́
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Lùlù rẹ kí n mọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakúkú rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakùkù rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ìlù mi kọ́ùn ni
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Rékọjá o máa lọ
Agberin_____Àríkijàn

Báyìí ni ẹranko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọjá tí ẹkùn sì ń kọ orin bákan náà. Nígbà tí ó kan ikùn láti kọjá, ẹ̀rù ti bẹ̀rẹ̀ sí bàa. Ẹkùn tún bẹ̀rẹ̀ orin rẹ̀ :

Ẹkùn________ Ríkíríkijàn
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ríkíríkijàn
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ aré
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ ayò
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Wọ́n ní á kànlù, mo kànlù
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Mo gbé ìlú mi s'àgbàlá
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọmọ ẹranko gbé e lọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Lùlù rẹ kí n gbọ́
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Lùlù rẹ kí n mọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakúkú rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakùkù rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ ìlù mi nùnun nì
Agberin_____ Àríkijàn

Bí ikùn tí gbọ́ pé ìlù ẹkùn ni òun gbé lọ́wọ́, pẹ̀ẹ̀ lójú ìlù sílè tí ó bẹ̀rẹ̀ sí sá lọ. Ẹkùn gbá tẹ́lẹ̀e,ṣùgbọ́n bí ẹkùn ṣe ni kí òun ó ki ikùn mọ́lẹ̀ ni ó ṣá wọ inú ihò lọ. Ikùn kò lọ láì f'arapa, èékánná ẹkùn ha ikùn ní ẹ̀gbẹ̀ méjèèjì. Bí ènìyàn bá rí ikùn lónìí, yóò rí pé ilà funfun wà ní ẹ̀gbẹ̀ méjèèjì ikùn di òní olónìí yìí o. Olè jíjà kò dára oooo

#EdeYorubaRewa

Ọfọ̀ Ẹ̀fẹ̀

"Dúró ń bẹ̀"
Ohun tá a wí f'ọ́gbọ́
Lọ́gbọ́ ń gbọ́
Èyí tá a wí f'ọ́gbà
Lọgbà ń gbà
Inú ẹtù kìí dùn
Kó wálé ọdún
Inú àgbọ̀nrín kìí dùn
Kò wálé dìsẹ́nbà
Aṣọ ìbora kìí lápò
Kèké kìí ya ilé epo
Ìgbín kìí fẹ́yìn rìn
Ọ̀kadà kìí ní kọ̀ndọ́
Ijọ́ tí ọmọdé bá gbé'rà lóko
Ní dé ilé
Ijọ́ tókèlé ba dọ́nà ọ̀fun
Ní I de ikùn
Mo pàṣẹ fún ọ
Óyá!!! Fi àtẹ̀jíṣé yìí ránṣé
Ẹ̀fẹ̀ lèyí àbí àwàdà.

#EdeYorubaRewa

Ọ̀RỌ̀ ìṣítí

Iṣu mi ọdún yìí
N kò ní fẹ́nìkan jẹ
Àgbàdo tí mo gbìn yìí
Kò ní kan ẹnìkan l'ẹ́nu
Ẹran ọ̀yà tí mo yìnbọn sí
Tíi mo ba ri
Emi nìkan ni yóò jẹ
Ko mọ̀ pé,
Ìgbẹ lẹran rẹ í gbé sí
Yorùbá bọ̀ wọ́n ní A kìí láhun ká nìyí
Ará ilé ahun ò gb'ádùn ahun
Ahun ọ̀hún
Ọ̀rọ̀ ìjìnlè Yorùbá lèyí
Ọmọ ahun, kò gbádùn ẹ
Ìyàwó ahun kò gbádùn ẹ
Gbogbo atótótu òkè yìí ń sàfihàn aburu
Tí ń bẹ nínú ahun ṣíṣe
Bó ṣe oúnjẹ lo ní, bó ṣe owó dákún ran aláìní lọ́wọ́
Àdáníkànje, ládánìkànku
Ẹni tó lawọ́
Kò tíì rí àánú Olódùmarè
Aánbọ̀sìbọ́sí ahun
Òkè lọ́wọ́ afúnni ń gbé
Ẹ jẹ ká jáwọ́ ahun ṣíṣe.
Ẹ má jee ká láhun nítorí ahun kò dára.
Bí ẹnikẹ́ni bá wá ìrànlọ́wọ́ dé ọ̀dọ̀ dákún gbìyànjú láti ràn wọ́n lọ́wọ́.

#EdeYorubaRewa.

Tuesday 22 August 2017

Ìkéde tí Ààrẹ Muhammad Buhari ṣe

Èyí ni ìkéde tí Ààrẹ Muhammad Buhari ṣe ní ọjọ́ kọkànlélógún, oṣù kẹjọ ọdún 2017 (21/08/2017).

Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà,

1) Mo dúpẹ́ fún Ọlọ́run àti gbogbo ọmọ orílè Nàìjíríà fún àdúrà yín, inú mi dùn láti padà sí orílè èdè Nàìjíríà tí mo tí jẹ Ààrẹ.

2) Dídúró mi ní orílè-èdè United Kingdom, gbogbo ohun tí ó ń lọ ní orílè èdè Nàìjíríà ni mo mọ. Àwọn ọmọ orílè èdè Nàìjíríà gbójú gbóyà láti sọ ohunkóhun, ṣùgbọ́n inú mi bàjé láti gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ mìíràn tí wọ́n ń sọ, pàápàá jù lọ lórí ẹ̀rọ ayélujára.

3) Ní ọdún 2003 lẹ́yìn ìgbátí mọ darapọ̀ mọ òṣèlú, Olóògbé olóyè Emeka Ojukwu wá sí ìlú mi ní Daura gẹ́gẹ́bí àlejò. A sọ̀rọ̀ ni kíkún nípa awon ìpèníjà tí orílè èdè Nàìjíríà ń dójú kọ fún ọjọ́ méjì tí Ilé sii sú báwa níbè. Àwa méjèèjì fi orí ọ̀rọ̀ wa kò wípé orílè èdè Nàìjíríà gbọdọ̀ wà ní Ìsòkan.

4) Ìsòkan orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ti ní ìyanjú kò sì ní ìdúnàdúrà nínú. Àko ní fi ààyè gba àwọn alaimokan láti dá wàhálà àti rògbòdìyàn sílè nítorí bí nkan bá bàjẹ́ tán, ńṣe ni wọn yíò sálọ tí wọn yíò sì jẹ́ kí ẹ̀jẹ̀ alaise ṣòfò.

5) Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó ní aàǹfààní láti gbé ayé àti láti lépa ohun rere tí wọ́n bá fẹ́ ṣe ni ibikíbi ni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láìsí ẹnì kankan tí yíò di wọn lọ́wọ́.


6) Mo nígbàgbọ́ wípé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó fi ara mọ́ èróngbà yìí.

 7) Eléyìí kìí ṣe láti di àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti má mọ ohun tí ó kàn wón. Ṣùgbọ́n ẹwà àti ifamora orílẹ̀ èdè gbọdọ̀ fi àyè gba onírúurú ẹgbẹ́ láti ṣisẹ́ kí orílè èdè yìí le tẹsiwaju.

8) Àwọn ilé ìgbìmò Asòfin àti ilé ìgbìmò ní àwọn ìlú kọ̀ọ̀kan ni ẹ̀tọ́ láti  gbìmọ̀ àti láti ṣe ìwádìí tí ó dára.

9) Ìlàkàkà àwọn ọmọ ilẹ̀ ìgbìmò náà ni wípé ó dára kí gbogbo wa máa gbé papọ ni ìrépọ̀ kí ó má sí ìpínyà láàrin wa.

10) Mo ń gbìyànjú láti má jẹ́ kí ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn bá  àwọn elétò ààbọ̀ látàrí àṣeyọrí tí wọ́n tí ṣe ni ọdún kan àti oṣù díè sẹ́yìn.

11) Wọ́n gbọdọ̀ lé Ìgbé sùnmọ̀mí àti ìwà ọ̀daràn jìnà kí ó le fún gbogbo wa ni àǹfààní láti gbé ní ayọ̀ àti àlàáfíà.

12) Fún ìdí yìí a gbọdọ̀ tún ṣòkòtò wa ṣán làti gbé ogun tí àwọn wọ̀nyí:

Agbé sùmòmí Boko Haram
Àwọn gbọmọgbọmọ, àwọn Darandaran àti àgbẹ̀ àti
Èdè àiyedè láàrin wa pẹ̀lú iranlọwọ àwọn olóṣèlú. A gbọdọ̀ dojú kọ wón.


13) Gbogbo olólùfẹ́ orílè èdè Nàìjíríà, ìsisẹ́ papọ wa yíò jẹ́ kí á le gbé ogun tí àwọn ìpèníjà wọ̀nyí:

·   Ètò ọrọ̀ ajẹ́

·     Ìdàgbàsókè ètò òṣèlú àwa araawa
·       Àti àlàáfíà tó yè kooro láàrin gbogbo ọmọ Nàìjíríà

14) Máa rí wípé gbogbo àwọn ìpèníjà yìí ni a borí wọn. Inú mi dùn láti padà sí orílè-èdè Nàìjíríà.

15) Ẹsẹ́ púpọ̀, Èdùmàrè a tún orílè èdè Nàìjíríà ṣe.

Àmín.

#EdeYorubaRewa

Tuesday 11 July 2017

Ọ̀RỌ̀ Ìkìlọ̀ 2

Ẹjẹ́ ká gb'áyé ṣe rere,
Ọjọ́ a kú làá dère,
Ènìyàn ò sunwòn láàyè,
Ǹjẹ́ a lè rí ohun gidi sọ nípa rẹ tó bá kú,
Àbí àwọn ènìyàn a máa sọ wípé àtún kú tún kúù rẹ lọrun,
Ẹjẹ́ ká gb'ayé ṣe rere,
Kí ọmọ aráyé lee rí ohun tó dára sọ,
Ẹjẹ́ ká kó pa láti tún, ilé, ọ̀nà, ìlú, orílè èdè wa ṣe,
Kí a kó ipa pàtàkì láwùjo wa,
kí ọmọ aráyé lee sọ nípa wa dára dára tí a bá kú,
Ní tèmi ooo rere lè mi o ṣe,
N ò ní ṣe ìkà,
kí ọmọ aráyé lee sọ ohun gidi nípa mi.

Ìwo ń kọ?

#EdeYorubaRewa

Ọ̀RỌ̀ Ìkìlọ̀

Ohun tá a ṣe ní kọ̀kọ̀
Táa fẹ́ ká ráyè mọ̀ nípa ẹ̀
Ohun tó dára ní,
Èyí táa ṣe ní kọ̀rọ̀
Táà fẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó rí
Ohun burúkú ni
Ṣùgbọ́n bó ò tafà sókè, tó o yídò borí
Bí ọba ayé ò rí ọ, tọ̀run ń wò ọ́
Ìwọ máa gbọ̀nà ẹ̀bùrú
Sọmọ ádámọ lọ́sẹ́
Lójú ilé ni elédùmarè ó gbà mú ọ
Ìwọ tó o ní kú lọ́wọ́
Tó o látaare
Ìwọ tó jẹ́ kìkì ìkà
Tó jẹ́ pẹ́nu to bá kàn ọ o kàn ìjàngbọ̀n
Máa ṣe nìṣó, ẹ̀san ń bọ̀
Rántí pé, ìwà tó o bá hu
Lọmọ máa débá
Ẹni tó gbèbù ìkà ọmọ rẹ yíò je àjeyó ìyà
Yíò je ajẹsẹ́kù dọmọ ọmọ
Ẹ jẹ́ ká gbélé ayé ṣe rere
Ká lè ní gbẹ̀yìn tó dùn.
Kò sí ohun tá a ṣe tí elédùmarè ò rí
Ẹ jẹ ṣe dára ní gbogbo ibikíbi tí a bá wà.



#EdeYorubaRewa

Sunday 25 June 2017

Àlọ́ Apá kejì

Àyipadà dé fún Ògbójú-ọdẹ ti ó di Ẹlẹ́mu tóó bẹ̀ ti àwọn ará ilú ṣe akiyesi àyipadà yi.  Yorùbá ni “ojú larí, ọ̀rẹ́ ò dénú”. Ìjàpá ọlọ́gbọ́n ẹ̀wẹ́ sọ ara rẹ̀ di ọrẹ kòrí kòsùn pẹ̀lú Ògbójú-ọdẹ nitori àti mọ idi ọrọ̀ rẹ.  Laipẹ, àrùn Ṣọ̀pọ̀ná bo Ògbójú-ọdẹ eleyi dá iṣẹ́ àti gbé ẹmu fún àwọn Ará Ọ̀run dúró.  Gẹgẹbi ọ̀rẹ́ ó bẹ Ìjàpá pé ki ó bá ohun bẹ̀rẹ̀ si gbé ẹmu lọ fún àwọn Ará Ọ̀run.  Ó ṣe ikilọ fún Ìjàpá bi ikilọ ti àwọn Ará Ọ̀run fi silẹ̀.  Ìjàpá, bẹ̀rẹ̀ si gbé ẹmu lọ, ni ọjọ́ keji ti ó ri owó rẹpẹtẹ ti àwọn Ará Ọ̀run kó si idi agbè ẹmu àná, ó pinu lati mọ idi abájọ.

Ìjàpá fi ara pamọ́ si igbó lati wo bi àwọn Ará Ọ̀run ti ńmu ẹmu. Ohun ti ó ri yàá lẹ́nu, ó ri Ori, Ẹsẹ̀, Ojú, Apá àti àwọn ẹ̀yà ara miran ti wọn dá dúró, ti wọn si bẹ̀rẹ̀ si mu ẹmu. Ìjàpá  bẹ̀rẹ̀ si fi àwọn Ará Ọ̀run ṣe yẹ̀yẹ́.  Nigbati wọn gbọ, wọ́n le lati pá ṣùgbọ́n, Ìjàpá sá àsálà fún ẹmi rẹ, ó kó wọ inú ihò, wọn kò ri pa.

Ògbójú-ọdẹ reti titi ki Ìjàpá kó owó ẹmu dé.  Nigbati Ìjàpá dé, ó gbé irọ́ kalẹ̀ pé olè dá ohun lọ́nà, wọn gba gbogbo owó ẹmu lọ ni ohun ṣe pẹ́.

Ara Ògbójú-ọdẹ ya, ó gbé ẹmu lọ fún ara-orun gẹgẹbi iṣe rẹ tẹ́lẹ̀ lai mọ iwà àkóbá ti Ìjàpá ti hù silẹ̀.

Àwọn Ará-Ọ̀run wọ ijàkàdi pẹ̀lú Ògbójú-ọdẹ, nitori ó rú òfin ikilọ ti wọn fun.  Nitori imọ̀ ti ó ni lẹ́nu iṣẹ Ọdẹ, Ará-Ọ̀run ko ri Ògbójú-ọdẹ pa.  Lẹhin ijàkàdi, ó ṣe àlàyé pé ara ohun ni kò yá, ó fi àpá han, pé nitori eyi ni ohun ṣe bẹ ọ̀rẹ́ ohun Ìjàpá ki ó bá ohun gbé ẹmu lọ fún wọn.

Wọn ṣe àlàyé ohun ti Ìjàpá ti ó pè ni ọ̀rẹ́ rẹ ṣe fún wọn.  Ará-Ọ̀run dariji Ògbójú-ọdẹ pẹ̀lú ikilọ pé ki o maṣe gbára lé ọ̀rẹ́. Wọn ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rẹ́ ò ṣé fi okùn ọlà han, nítorí ọ̀pọ̀ ọ̀tá ló ńṣe bi ọ̀rẹ́ nitori àti jẹ.

Ẹsẹ́ púpọ̀ fún ìfojúsọ́nà yín.
#EdeYorubaRewa


Àlọ́ Apá kinni

Ọkunrin kan wa láyé àtijọ́, Ògbójú-ọdẹ ni, ṣùgbọ́n bi ó ti pa ẹran tó, kò fi dá nkan ṣe.  Ọ̀pọ̀ igbà, ki ri ẹran ti ó bá pa tà, o ma ńpin fún ará ilú ni.  Nigbati kò ri ẹran pa mọ́, ó di Ọdẹ-apẹyẹ.

Ni ọjọ kan, ògbójú-ọde yi ri ẹyẹ Òfú kan, ṣùgbọ́n ọta ibọn kan ṣoṣo ló kù ninú ibọn rẹ.  Gẹgẹbi Ògbójú-ọdẹ, o yin ẹyẹ Òfú ni ibọn, ọta kan ṣoṣo yi si báa.  Ó bá wọ igbó lọ lati gbé ẹyẹ ti ó pa, lai mọ̀ pé ẹyẹ yi kò kú.  Ó ṣe akitiyan lati ri ẹyẹ́ yi mu, kẹ̀rẹ̀kẹ̀rẹ̀ ó bẹ̀rẹ̀ si wọ igbó lọ titi tó fi ṣi ọ̀nà dé ilẹ̀ àwọn Ará Ọ̀run àwọn ti wọn ńpè ni Abàmi-ẹ̀dá.

Inu bi àwọn Ará Ọ̀run nitori Ògbójú-ọdẹ yi jálu ipàdé wọn.  Wọn gbamú, wọn ni ki ó ṣe àlàyé bi ó ṣe dé ilẹ̀ wọn ki àwọn tó pá.  Ọdẹ ṣe àlàyé ohun ti ojú rẹ ti ri nipa iṣẹ́ àti jẹ àti gbogbo ohun ti ojú rẹ ti ri lẹ́nu iṣẹ́ ọdẹ.  Àwọn Ará-Ọ̀run ṣe àánú rẹ, wọn bèrè pé ṣe ó lè dá ẹmu, ó ni ohun lè dá ẹmu diẹ-diẹ.  Wọn gbaa ni iyànjú pé ki o maṣe fi ojú di iṣẹ kankan, nitori naa, ki ó bẹ̀rẹ̀ si dá ẹmu fún àwọn.

Wọn ṣe ikilọ pe, bi ó bá ti gbé ẹmu wá, kò gbọdọ̀ wo bi àwọn ti ńmu ẹmu, ki ó kàn gbé ẹmu silẹ ki o si yi padà lai wo ẹ̀hin.  Bi ó bá rú òfin yi, àwọn yio pa.  Ọdẹ bẹ̀rẹ̀ si gbé ẹmu lọ fún ara orun.  Bi ó bá gbé ẹmu dé, a bẹ̀rẹ̀ si kọrin báyìí:

Ará Ọ̀run, Ará Ọ̀run------------ Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Ará Ọ̀run, Ará Ọ̀run o,---------- Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Ki lo wá ṣe n’ilẹ̀ yi o-------------- Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Ẹmu ni mo wá dá,----------------- Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Èlèló lẹmu rẹ------------------Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Ọ̀kànkàn ẹgbẹ̀wá,-----------------Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Gbẹ́mu silẹ ko maa lọ------------Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Ará Ọ̀run, Ará Ọ̀run o,----------------Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbàaa

Lẹ́yìn èyi á gbé ẹmu silẹ á yi padà lai wo ẹ̀hin gẹgẹ bi ikilọ Ará Ọ̀run. Ni ọjọ́ keji, á bá owó ni idi agbè ti ó fi gbé ẹmu tàná wá.
Ẹ kú ojú lọ́nà fún ìyókù.

#EdeYorubaRewa


Monday 29 May 2017

Ayẹyẹ ìjọba tiwantiwa

Ó pé ọdún kejìdínlógún tí orílè èdè Nàìjíríà tí ń lo ìjọba tiwantiwa leyin igba ti ológun tí ń darí wá.

Mo kí gbogbo àwọn ọmọ orílè èdè Nàìjíríà nílé lóko àti lẹ́yìn odi wípé a kú ayẹyẹ ìjọba tiwantiwa (Happy Democracy day). Mo mọ wípé inú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni o dùn látàrí bí nkan ṣe rí, ẹ jẹ́ kí a nígbàgbọ́ ni àwọn tí ó wà lórí ipò báyìí wípé wọn a mú wa dé èbúté ògo.

"Ọ̀rọ̀ Yorùbá kan ló sọ wípé sùúrù kìí pọ̀ jù àfi tí kò bá ní tó."
Mo mọ wípé ìjọba tí a ní lori ipò báyìí ń gbìyànjú láti jẹ́ kí orílè èdè Nàìjíríà dara,ki o rọrùn fún tolórí telémù,Ǹkan tí ó ti bá jẹ́ fún ọdún mẹ́tadínlógún kólé ṣe ẹ túnṣe láàrin ọdún díè tí àwọn ìjọba yìí dé ibè ìdí nì tí ó fi ye ká ní sùúrù.
Ìjọba  Nàìjíríà,  ẹ bá wà tún orílè èdè wa ṣe, ẹsẹ àtúnṣe sì gbogbo ohun tí oti bàjé kí inú àwọn tí ó dibo fún yín lé dùn.

Iṣẹ́ wa lọ́wọ́ àwa náà tí a jẹ́ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà, lábé bí ó ti wù kí ó rí Ẹjẹ́ kí àwa náà rán ìjọba lọ́wọ́ látàrí kí a jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn rere

Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ẹ jẹ ká ní sùúrù àti èmi ìfaradà fún Ààrẹ Muhammad Buhari àti gbogbo àwọn tí ó kó sódì kí wọn lè mú wa dé èbúté ògo.

Dídára orílè èdè Nàìjíríà ó wà lọ́wọ́ èmi àti ìwọ ẹ jẹ́ kí á jọ ṣe.orílẹ̀ èdè Nàìjíríà yíò dára tí ó bá dára tán kí wọn má fi wa ṣe àwátì

🇳🇬🇳🇬🇳🇬🇳🇬🇳🇬
Semiat Olufunke Tiamiyu
#EdeYorubaRewa



Thursday 25 May 2017

Ìtàn òwe Yorùbá

Ìtàn tí ó rò mó òwe Yorùbá yìí,

                   "Kí lo rí l'ọ́bẹ̀ tí fi waaro ọwọ́."

Ní bí ọdún díè sẹ́yìn, ìlú kan wà tí wọ́n ń pè ní Kuo, ó wá ní Bode Saadu ni Ìpínlẹ̀ Kwara ṣùgbọ́n ìlú tí à ń sọ yìí jóná ni ọdún 1814.

Gbogbo Yorùbá kó ló máa ń lo òwe yìí tẹ́lẹ̀, ogun ni ó sì fà á tí òwe yìí fi wáyé.
Ìlú tí a ń pè ní Kuo yìí ni olórí tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Sholá Gberú. Nígbà tí ìlú Kuo jóná Sholá Gberú kò gbogbo àwọn ọmọ, ẹrú àti gbogbo ohun tí wọ́n ni lọ sí ìlú Ilorin,nígbà náà afonja wa láyé. Ìlú kan wà láàrin Ọ̀yọ́ àti Ilorin,ìlú Gbógun ni ìlú náà ń jẹ́, tí ogún bá sì fẹ́ ja Ọ̀yọ́ wọn gbodo kọ́kọ́ ja ìlú Gbógun tí à ń Wiyi. Nígbà tí wọ́n fẹ́ kogun ja ìlú Gbógun ALÁNÀMÚ ni lèdí àpò pọ̀  láti kogun ja ìlú Gbógun.


Arákùnrin tí wọ́n ń pè Alánàmú Pankere ní o ma ń fi jà, tí ó bá ti fi náà ẹni tí wọ́n dìjọ ń jà fi ń jà, ẹni náà ara rẹ̀ yíò wálè yíò sì na'wọ́ mú ẹni náà ìdí rẹ tí wọ́n fi ń pe ni ALÁNÀMÚ.
Alánàmú sì so ọwọ́ pò mo Ilorin, wọn sì mú orí ìyàwó ọ̀pẹ̀lẹ̀ mó ara, Wọ́n fún ní májẹ̀lé pé kí ó fi si inú oúnjẹ. Wọ́n rán àgbà ọmọ Sholá Gberú sí ọ̀pẹ̀lẹ̀, ìyàwó ọ̀pẹ̀lẹ̀ dáná oúnjẹ, ó sì ti fi májẹ̀lé si inú ounje náà, ọ̀pẹ̀lẹ̀ àti ọmọ Sholá Gberú tí fọ ọwọ́, bí ọmọ Sholá Gberú tí bu òkèlè pé kí ohun fi kan ọbẹ̀
Ó bá wararo ọwọ́. Ọ̀pẹ̀lẹ̀ bíi pé kí lórí l'ọ́bẹ̀ tí ó fi wararo ọwọ́, ló bá ní májẹ̀lé rẹ nínú ọbẹ̀.....
Báyìí ni Ọ̀pẹ̀lẹ̀ ni Bí kú ilé ọ bá pani tode ó lè pani.

Ìtàn tí ó rò mó òwe KÍ LO RÍ L'Ọ́BẸ̀ TÍ Ó FI WAARO ỌWỌ́. májẹ̀lé ni ó rí l'ọ́bẹ̀ tí ó fi Wararo ọwọ́.

Mo lérò wípé ẹ gbádùn ìtàn yìí.

#EdeYorubaRewa


Sunday 14 May 2017

Ìtàn ránpé.




E bá Ẹfọ̀n l'ábàtà, ẹ yọ Ọ̀bẹ tí, Omi le rò wípé ó mu kú ni?

Ìtùmò Òwe yìí: a kìí kánjú tàbí yára sí àwọn aàǹfààní tí a bá rí nítorí ó lè jẹ́ iṣẹ́ takuntakun tí ẹnìkan tí ṣe.

Ìtàn ránpé tí ó rò mó Òwe yìí.

Ní ayé àtijó bàbá ọdẹ kan wà, bàbá yìí tí ń de ìgbẹ́ fún ọ̀sẹ̀ díè ṣùgbọ́n kò rí ẹran kankan pa. Nígbà tí ó ṣe èdùmàrè jẹ́ kí ó rí ẹran Ẹ̀fọ̀n, ó yin Ẹfọ̀n yìí ni Ìbon ṣùgbọ́n ìbon yìí kò pá Ẹfọ̀n yìí kíákíá leyi tí ó mú kí Ẹfọ̀n yìí sálọ. Bàbá ọdẹ yìí ri ó sì rántí pé ohun kò ní ohun jíjẹ fún ọjọ́ díè sẹ́yìn, èyí sì mu kí bàbá ọdẹ yìí wá Ẹfọ̀n pẹ̀lú ìgbàgbọ́ pé ìbọn tí ó bá ó ti pá. Lẹ́yìn ọjọ́ díè, Ẹfọ̀n yìí kú sí àgbàlá ẹnikẹ́ni nínú abúlé, kí bàbá ọdẹ yìí tó dé ibè àwọn ènìyàn abúlé náà tí rí wípé Ẹfọ̀n tí kú sí inú àgbàlá wọn leyi tí wọ́n rò wípé òrìṣà àti Baba ńlá àwọn ni ó see

Gbogbo ènìyàn sì lọ sí ibi tí Ẹfọ̀n yìí kú sí pẹ̀lú Ọ̀bẹ láti pín láàrin ara wọn, ṣùgbọ́n kí wọ́n tó bẹrẹ si maa ge bàbá Ọdẹ yìí dé ibè ó sì dá wọn dúró ní o bá sọ wípé "E bá Ẹfọ̀n l'ábàtà, ẹ yọ Ọ̀bẹ tí, Omi le rò wípé ó mu kú ni?"

Mo lérò wípé ìtàn ránpé yìí ni ìtumò sí yín.
Ẹsẹ́ púpọ̀
Ẹ kú ojú lọ́nà fún tí ọjọ́ méjo..
#EdeYorubaRewa

Tuesday 9 May 2017

Òrùn Ati Òṣùpá

Ìtàn Òrùn Ati Òṣùpá fún àkà gbádùn yín......
nígbà ìwásẹ̀, ọba ọdẹ Ọ̀run níse alákoso ohun gbogbo, ìkáwọ́ rẹ̀ ṣì ni gbogbo ohun tí a dá wà.ọba ọdẹ Ọ̀run ní ìyàwó , ósì tún bí ọmọ méjì. ÒRÙN àti ÒSÙPÁ ni ọmọ méjì tí ọba ode ọ̀run bí. Òrùn àti òsùpá fẹ́ràn ara wọn gidigidi, tí ó jẹ́ wípé bí òsùpá ò bá ṣí nílé òrùn kòní jẹun àfi ìgbà tí òsùpá bá dé ,bẹ́ẹ̀ nọ sì ni òsùpá bí òrùn kò bá dé kò ní jẹun.
Ní ọjọ́ kan ọba ọdẹ ọ̀run ránsé sí òṣùpá àti òrùn ọmọ rẹ wìpè kí wọn wà rí òhun. nígbàti wọn dé bè , ọba ọdẹ ọ̀run sọ fún wọn wípé òhun fẹ rìn irìnàjò kan tí yóò sì pẹ́ kí òhun tó padà , óní kí òṣùpá àti òrùn lọ fi oríkorí kí wọn se àpérò ẹni tí yóò delé de òhun tí òhun bá wà ní ìrìnàjò. Wọ́n dúpé lọ́wọ́ bàbá wọn, wọn sì se ìlérí láti se gẹ́gẹ́ bí bàbá wọn ti sọ.
Ní ọjọ́'rù ọ̀sẹ̀ kan náà, òṣùpá àti òrùn fi ojú kan ra, sùgbón ọ̀rọ̀ ò wọ̀ láàrín àwọn méjèèjì lérí ẹni tí yóò délé nígbàtí bàbá wọn bá lọ. òṣùpá ní òhun ọkọ ẹgbàágbèje ìràwọ̀ ni yóò delé de bàbá àwọn, béèni òrùn tutọ́ sókè fojúgbàá wípé òhun ìmólè ọmọ aráyé ni yóò delé de bàbá àwọn , óní láì sí èmi òrùn inú òkùnkùn biribiri ni ayé kò bá wà,ó ní èmi àfi ojojúmó dára bí egbin, òsùpá sọ wípé tí o bá rí béè ọmọ aráyé òní máà sọ wípé isẹ́ lò òsùpá se lájùlé òrùn, óní òhun ni yóò delé de bàbá wọn.
Bí wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀ náà bí ẹni gba igbá ọtí re ,títí ó fi di ìjà. òsùpá lu òrùn ní ìlú ẹni lu bàrà, òrùn náà sí lu òsùpá bákan náà.
nígbátì bàbá wọn gbọ́ sí ọ̀rọ̀ náà inú rẹ bàjé,óní kí wọ́n pe àwọn méjèèji wá sí àgbàlà olódùmarè,ní ibẹ̀ ló ti jẹ kóyé wọn wípé òhun ọba ọdẹ ọ̀run ní se alákòso ọ̀sán àti òru,óní ní ìdí èyí òhun yóò pin ìlú náà sí méjì,óní kí òṣùpá máà jọba lérí òru , ósì ní kí òrùn máà jọba lóri ọ̀sán wọn kò sì gbọdọ̀ fi ojú kan ra gẹ́gẹ́ bí ìjìyà ẹ̀sẹ̀ wọn.
Ní ọjọ́ yíí inú òṣùpá àti òrùn bàjẹ́ nítorí wọn kòní fo jú kan ra mọ́ àti wípé àyè àti má se bí ẹbí ti dópin. Ìgbà kúgbá tí òrùn àbí òṣùpá báti rántí ìdájó yii ,nínú ọdún wọn a máa sunkún lọ́pọ̀lọpọ̀ ,ekún wọ̀nyí ni àwa ọmọ ènìyàn ńpè ní ÒJÒ.
#Ìbéèrè
Kíni Èkó Inú Ìtàn Yìí?
#EdeYorubaRewa




Ọ̀RỌ̀ ÌDÚPẸ́

Kíni mo jẹ́? Tani ni mí? Tí Kò bá sí èyin, kò lè sí ojú ìwé #EdeYorubaRewa. Yorùbá bò wọn ní "Àgbáj'ọwọ́ la fi ń sọ̀'yà, Àjèjí ọwọ́ kan kò gbẹ́'rù dó'rí" leyi tí ó túmọ̀ sí wípé ọlá Ọlọ́run àti ọlá gbogbo olólùfẹ́ Èdè Yorùbá Rẹwà ni ó fún mi ní agbára láti máa ṣe ohun kékeré tí mò ń ṣe láti gbé èdè Yorùbá lárugẹ.... Mọ wá dúpẹ́ púpọ̀ lọ́wọ́ gbogbo àwọn tí wọ́n fẹ́ràn àti àwọn tí wọ́n tẹ́lẹ̀ wa lórí ẹ̀rọ ayélujára Facebook, Twitter, Instagram, Blog àti WhatsApp,èdùmàrè ò ní paná ìfẹ́ wá.
Mo sì tún fi àsìkò yìí dúpẹ́ lọwọ gbogbo àwọn tí wọ́n ni ìgbẹ́kẹ̀lé dáadáa nínú wa ti wọ́n sì fi ìfẹ́ báwa ra aṣọ tí a ṣe láti fi ṣe ayẹyẹ ọdún kan, elédùmarè a nífẹ̀ẹ́ gbogbo yín ooo.
Mo wá ro gbogbo àwọn tí wọ́n ra aṣọ náà kì wọn ó fi àwòrán wọn ránṣé sí mi láti lè fi sì ojú ìwé EdeYorubaRewa
Ẹsẹ́ púpọ̀
#EdeYorubaRewa

Tuesday 18 April 2017

Ayeye odun kan

ifọrọwanilẹnuwo....
                                                             1) #Kiniorúkọyín?
Orúkọ mi Semiat Olufunke Tiamiyu, ọ̀kan lára àwọn olùdarí ojú ìwé Èdè Yorùbá tí ó rẹwà.
                                                          2) #KíniEńṣelónìí?
A ń ṣe ayẹyẹ wípé ojú ìwé Èdè Yorùbá tí ó rẹwà pé ọdún kan tí a ti gbé kalẹ̀.
                                                         3) #kílegbàléròtíẹfidáojúìwéyìísílè?
Ohun tí mo gbà lérò pò, máa kàn sọ díè nínú è
1) Ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tí a ti wá ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn òbí àti alágbàtọ́ ni ó jé wípé tí ẹ bá lọ kíwọn tí ẹ ń sọ Yorùbá ohun tí wọ́n àá sọ ní wípé ẹ má sọ Yorùbá sí àwọn ọmọ yìí.
2) Ní orílẹ̀ èdè United Kingdom tí mo wà, tí èmi àti àwọn ọ̀rẹ́ tí wọn jẹ́ Yorùbá bá jọ jáde wọ́n á ní kí n má sọ Yorùbá nítorí pé Yorùbá mi ti kijú (strong Yorùbá accent). Ẹyin máa ń bà mí nínú jẹ́ púpọ̀ débi wípé mo yẹra fún àwọn ọ̀rẹ́ wọ̀nyí.
3) ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ Yorùbá ti ó jé wípé ó kọ ilà (Tribal mark) sí ojú wọn ní orílẹ̀ èdè United Kingdom ti mo bá kí irú ẹni bẹẹ pẹ̀lú èdè Yorùbá, èdè Gẹ̀ẹ́sì ni wọn a fi dáhùn. Lẹ́yìn tí ó burú jáì. Ìwọ̀nyí àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìrírí mi ni ó faa tí a fi dá ojú ìwé yìí sílè.
4) Nígbàtí mo wà ní ilé ìwé alákòbẹ̀rẹ̀ àti gírámà àwọn olùkọ́ wá a máa sọ wípé ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ sọ Yorùbá wọn àá sì ma pèé ni (Vernacular) ẹnikẹ́ni tí ó bá sọọ wọn fi ìyà jẹ ọmọ bẹẹ.
                                         4) #KíẹléròpéaleṣetíèdèYorùbákòfiníparun?
Ohun tí a lè ṣe pọ̀;
1) Àwọn òbí àti alágbàtọ́ ni wọ́n ní iṣẹ́ láti ṣe látàrí mi má sọ èdè Yorùbá sí àwọn ọmọ wọn.
2) Àwọn ìjọba wa ni láti gbé ètò kan kalẹ pàápàá jù lọ fún àwọn ilé ẹ̀kọ́ aladani láti máa kọ èdè Yorùbá ní ilé ìwé wọn, kí wọn sì tún máa lò ó ti ẹnikẹ́ni bá fẹ́ wo ilé ìwé gíga (University).
3) Èmi àti ìwọ náà ni iṣẹ́ láti ṣe látàrí mi máa wọ aṣọ ilé wa, oúnjẹ ilé wa àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn àṣà àti ìṣe ilé Yorùbá.
                                                                       #Ìdúpẹ́:
Àkókò mo dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run ti o fún mi ní iwonba ọgbọ́n àti ìmò nípa èdè Yorùbá, mo tún dúpẹ́ lọ́wọ́ àwọn òbí mi àti mọ̀lébí pàápàá jù lọ ìyá ìyá mi (Grandmother) tí ó ti kú báyìí (kí Ọlọ́run bá mi fi ọ̀run ke), mo tún dúpẹ́ lọ́wọ́ Adé orí mi Mubarak Damilare Tiamiyu fún atileyin àti ìwúrí tí wọ́n ṣe fún. Mo wá dúpẹ́ lọ́wọ́ gbogbo olólùfẹ́ ojú ìwé yìí tí wọ́n tí ń tẹ́lẹ̀ wá láti ọjọ́ kìíní títí di òní, mo gbaa ladura wípé èdùmàrè òní pa iná ìfẹ́ wa, èdè Yorùbá náà o sì ni parun.




Monday 17 April 2017

Àlọ́ yìí dá lórí Ilẹ̀ Àti Ọlọ́run.

Àlọ́ ooo 
Àlọ́ ọọọ 
Àlọ́ yìí dá lórí Ilẹ̀ Àti Ọlọ́run. 



Ní ayé àtijó, ọ̀rẹ́ ni ilẹ̀ àti Ọlọ́run. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ibùgbé wọn jìnà sí ara wọn, àwọn méjèèjì a máa wá ara wọn. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ni Ọlọ́run máa ń sọ̀kalẹ̀ láti wá bá ilẹ̀ ṣeré. Ní ọjọ́ kan, àwọn méjèèjì pinnu láti dè'gbẹ́ lọ kí àwo lè pa ẹran. Wọ́n dẹ ìgbẹ́ títí, eku ẹmọ́ kan ni wọ́n rí pa. Ọlọ́run sọ wípé òun lẹ̀gbọ́n, nítorí ìdí èyí, òun ni òun yíò mú èyí tó pọ̀ níbẹ̀. Ilẹ̀ náà fàáké kọ́rí ó ní òun ni àgbà tí ó gbọ́dọ̀ mú èyí tí ó pọ̀. Ìjà yìí pọ̀ títọ tí Ọlọ́run fi bínú lọ sí ọ̀run tí ilẹ̀ náà sì bínú lọ. Kí ló wá ṣẹlẹ̀ ni pé òjò kọ̀ kò rọ̀, àgbàdo pọ̀n'pẹ́ kò gbó,ọmọge lóyún oyún gbẹ mọ́ wọn lára, akérémọdọ̀ w'ẹ̀wù ìràwé. Iyán yìí mú títí tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn bẹ̀rẹ̀ síí kú.

Nígbà tí ó ṣe, ọba ìlú wá eéjì kún ẹẹ́ta, ó lọ oko aláwò. Babaláwo sọ fún un pé wọn gbọdọ̀ ṣe ètùtù. Ohun tí wọn yíò ṣe náà ni kí wọn gbé ẹbọ ló sí ọ̀run. Kò sí ẹni tí ó yọjú láti gbé ẹbọ yìí bí kò ṣe ẹyẹ Igún. Igún gbé ẹbọ ó di ọ̀nà ọ̀run. Ṣùgbọ́n bí ó ti ń lọ ní ó bẹ̀rẹ̀ sí kọrin báyìí pé:

Igún:_________Olúnréte
Elégbè:_______Àjànréte jàà
Igún:_________Olúnréte
Elégbè:_______Àjànréte jàà
Igún:_________Ilé ohun Ọlọ́run
Elégbè:_______Àjànréte jàà
Igún:_________ Wọ́n p'eku ẹmọ́ kan
Elégbè:_______Àjànréte jàà
Igún:_________Ọlọ́run L'óun l'ẹ̀gbọ́n
Elégbè:_______Àjànréte jàà
Igún:_________Ilé L'óun l'àgbà
Elégbè:_______Àjànréte jàà
Igún:_________Ọlọ́run bínú ó lọ
Elégbè:_______Àjànréte jàà
Igún:_________Ilé bínú ó lọ
Elégbè:_______Àjànréte jàà
Igún:_________ Àgbàdo pọ̀n'pẹ́ kò gbó
Elégbè:_______Àjànréte jàà
Igún:_________ọmọge lóyún oyún gbẹ
Elégbè:_______Àjànréte jàà
Igún:_________Olúnréte
Elégbè:_______Àjànréte jàà

Bí igún ti gbé ẹbọ dé ọ̀run ni Ọlọ́run gba ẹbọ náà. Èyí jásí pé ẹbọ fín, ẹbọ dà. Bí igún tí gbé ẹbọ ṣílẹ̀ tán tí ó ń bọ̀ wá sí ilé ayé ni òjò bá bẹ̀rẹ̀ sí rọ̀. Òjò yìí l'ágbára púpọ̀ tí ó fi jẹ́ pé gbogbo àwọn ẹyẹ ni wọ́n ti ilẹ̀kùn ilé wọn mọ́ orí. Nígbà tí igún dé, òjò ti gbé ilé rẹ, kò sì rí ibi tí yíò yà sí tàbí f'arapamọ́ si. Ohun tí ó tún wá burú ni pé bí ó bá ti fẹ́ yà sí ilé ẹyẹ kan ni ẹyẹ yìí ó saajẹ ní orí. Àwọn ẹyẹ ṣe eléyìí títí orí igún fi pá títí di òní yìí.

Àlọ́ yìí kọ́ wa wípé kò yẹ kí a fi ibi san oore. Oore ni igún ṣe, ibi ni wọ́n fi ṣan fún un.

#EdeYorubaRewa

Sunday 9 April 2017

Ìjàpá àti Àna Rẹ̀



Àlọ́ ooo
Àlọ́ ọọọ
Àlọ́ yìí dá lórí #ÌjàpáàtiÀnaRẹ̀
Gbogbo wa ni a ti mọ Ìjàpátìrókò ọkọ Yánníbo gẹ́gẹ́ bí #ọlọ́gbọ́nẹ̀wẹ́ àti #ọ̀kánjúà tí ó sì tún jẹ́ #Tìfunlọ̀ràn.
Ní ọjọ́ kan Ìjàpá gba ilé àna rẹ̀ lọ láti lọ kí wọn. Nígbà tí ó dé ilé àna rẹ̀, wọ́n ṣe #àpọ́nlé rẹ̀ dáadáa. Ṣùgbọ́n bí wọ́n ṣe ṣe aájò Ìjàpá tó, ìwà rẹ̀ kò padà. Ìjàpá rí pé àwọn àna òun ń ṣe ẹ̀wà lórí iná. Ìjàpá ń rò nínú ara rẹ̀ ọ̀nà tí yíò fi bu díè nínú ẹ̀wà náà lọ sí ilé rẹ̀. Dípò kí Ìjàpá tọrọ ẹ̀wà lọ́wọ́ àna rẹ̀, ṣe ni ó ń rò bí yíò ṣe jí nínú ẹ̀wà náà.
Ìjàpá wo yányànyán kò rí ẹnìkankan ni ó bá rápálá lọ sí ibi tí wọ́n ti ń ṣe ẹ̀wà tí ó sì ń hooru yèèè. Ìjàpá bu díè nínú ẹ̀wà gbígbóná sí inú fìlà rẹ̀, ó sì dée m'órí. Nígbà tí ó ṣe, ẹ̀wà bẹ̀rẹ̀ sí jó Ìjàpá lórí ni ó bá sọ fún àna rẹ̀ pé òun ń lọ sí ilé òun. Àna Ìjàpá sì pinnu láti sìnín sí ojú ọ̀nà Ìjàpá rọ àna rẹ̀ títí kí ó má sin òun ṣùgbọ́n àna rẹ̀ kọ̀ jálẹ̀ pé òun ni lati paá lẹ́sẹ̀ dà.
Bí wọ́n ṣe rìn díè ni ooru ẹ̀wà bẹ̀rẹ̀ sí jó Ìjàpá ní orí. Nígbà tí kò le f'ara dàá mọ́ ni ó bá ti orin bọnu báyìí pé;
Ìjàpá:__________Àna mi mo ní o padà lẹ́yìn mi
Ègbè:__________Ooru ẹ̀wà ń jó mí lórí foofáá
Ìjàpá:__________Àna mi mo ní o padà lẹ́yìn mi
Ègbè:__________Ooru ẹ̀wà ń jó mí lórí foofáá
Ìjàpá:__________Àna mi mo ní o padà lẹ́yìn mi
Ègbè:__________Ooru ẹ̀wà ń jó mí lórí foofáá
Nígbà tí Ìjàpá rí i pé òun kò le mú mọ́ra mọ́ ni ó bá sí fìlà lórí tí ẹ̀wà gbígbóná sì dà sílè fún ìyàlẹ́nu àna Ìjàpá. Ki Ìjàpá tó sí fìlà ooru ẹ̀wà tí bó Ìjàpá lórí. Ojú tí Ìjàpá púpọ̀ ní ọjọ́ yìí.
Èyí ló sì mú kí orí Ìjàpá ó pá títí di òní yìí.
Ìtàn yìí kọ́ wa wípé ojú kòkòrò kò dára.

Tuesday 4 April 2017

Ìjàpá àti Ajá


Àlọ́ ooo
Àlọ́ ọọọ
Àlọ́ yìí dá fìrìgbagbò
Ó dá lórí #ÌjàpátìrókòọkọYánníbo àti #Ajá
Ní ìlú kan ni ayé àtijó, àwọn ẹranko méjì kan wà tí wọ́n jẹ́ ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́. Àwọn ọ̀rẹ́ méjì náà ni Ìjàpátìrókò ọkọ Yánníbo àti Ajá. Iyàn mú púpọ̀ ní ìlú yìí débi wípé gbogbo igi wọ́wé tán, àgbàdo kọ̀ kò gbó, àwọn ọlọ́mọge lóyún, oyún gbẹ mọ́ wọn lára. Gbogbo akérémọdò wọ ẹ̀wù ìràwé. Iyàn náà mú gan-an ni. Ṣùgbọ́n bí Iyàn tí mú tóo, Ajá kò mọ Iyàn kankan, ṣe ni ara rẹ̀ ń dán yọ̀ọ̀. Bí Ajá ṣe ń dán tí ó tún sanra nínú Iyàn yìí ń kọ Ìjàpá lóminù. Ìjàpá bẹ̀rẹ̀ sí ro ohun tí yíò ṣe.
Nígbà tí ó ṣe Ìjàpá tọ ọ̀rẹ́ rẹ̀ Ajá lọ. Ó bẹ̀ẹ́ pé kí ó dákun ṣàánú òun kí ebi má lu òun àti àwọn ẹbí òun pa. Ajá sọ fún Ìjàpá pé kò wu òun náà kí ebi máa paa ṣùgbọ́n ìwà àgàbàgebè rẹ̀ ni kó jẹ́ kí òun sọ àṣírí ibi tí òun ti ń rí oúnjẹ jẹ. Ìjàpá bẹ Ajá pé òun kò ní dá'lẹ̀, àti pé òun yíò fi ọwọ́ sí ibi tí ọwọ́ gbé.
Nígbà tí ẹ̀bẹ̀ pọ̀, Ajá gbà láti mú Ìjàpá lọ. Ajá mú Ìjàpá lọ sí oko iṣu kan tí a kò mọ ẹni tí ó ni oko náà. Bí wọ́n ṣe dé'bẹ̀ ni Ajá wa iṣu tí ó lerù, ó sì ti múra láti padà sílé. Ṣùgbọ́n ní ti Ìjàpá, ó wa iṣu títí ilẹ̀ fi kún. Nígbà tí ó dìí, ó rí wípé òun kò le gbé, ó ti pọ̀ jù èyí tí òun lè gbé lọ. Ajá bẹ̀rẹ̀ sí pariwo kí ó yára ṣùgbọ́n ọ̀kánjúà ojú rẹ̀ kò jẹ́ kí ó gbọ́ igbe Ajá. Ajá bá bẹ̀rẹ̀ si kọ orin:
Ajá:_________ Ìjàpá dì mọ ń bá
Agbeorin:____ Teremọ́bá-teremọ̀bà tere
Ajá:________ bí ó bá dì mọ́ n ba; Ma súré sẹ́sẹ́ p'oloko; Ma rìnrìn gbẹ̀rẹ̀ pọlọ́jà Ma sòkú ọlọ́jà l'égbèje
Agbeorin:______Teremọ́bá-teremọ̀bà tere
Bí Ajá ṣe ń kọ orin yìí ni ó ń sáré lọ tete, nígbà tí Ìjàpá ń bá iṣu tí ó dì kalẹ̀ yí. Níbi tí Ìjàpá tí ń bá ẹrú iṣu ja ni olóko dé tí ó sì mú Ìjàpá lọ sí ilé Ọba. Ní ilé Ọba, Ìjàpá jẹ́wọ́ pé Ajá ni ó mú òun lọ sí inú oko tí àwọn tí lọ jí iṣu wà. Bí Ajá tí dé ilé ni ó ti mọ̀ pé wàhálà tí dé, ó dá ọgbọ́n, ó di ẹyin adìye sí kọ̀rọ̀ ẹ̀rẹ̀kẹ́ méjèèjì, ó sì ṣe bí ẹni tí ara rẹ̀ kò yá, ó pirọrọ bí ẹni tí ó sùn lọ. Ọba si pàṣẹ pé kí wọ́n lọ mú Ajá tí wọ́n jíṣẹ́ fún un pé ọba ń pè é, ó fi ẹyin tẹ ọkàn nínú ẹyin tí ó fi sí kọ̀rọ̀ ẹ̀rẹ̀kẹ́, ẹyin fọ́, ó sì dà sílè bí ẹni tí èébì gbe. Wọ́n mú Ajá dé ilé ọba ní àpàpàǹdodo. Bí wọ́n ṣe dé ilé ọba tí ọba sì bí léèrè bóyá òun ni ó mú Ìjàpá lọ jí iṣu wà lóko olóko, Ajá ní kí í ṣe òun torí pé òun ti ń ṣe àìsàn fún bíi ọ̀sẹ̀ kan. Bí ó sì ti wí báyìí ni ó tún fi eyín tẹ ẹyin tí ó wà ní kọ̀rọ̀ ẹ̀rẹ̀kẹ́ kejì ó sì dà sílè gọ̀ọ̀rọ̀gọ̀, ó dà bí pé Ajá ń bì. Ọba gba ohun tí Ajá sọ pé ara òun kò yá fún bí ìgbà díè. Ọba wá pàṣẹ pé kí wọ́n ti ojú Ìjàpá yọ idà, kí wọ́n sì ti ẹ̀yìn rẹ̀ ti bọọ.
Ìtàn yìí kọ́ wa wí pé kò yẹ kí á máa ṣe àṣejù sì gbogbo nǹkan.

Monday 6 March 2017

ọmọbìnrin Alaáìgbọ́ràn

Àlọ́ rèé o fún gbogbo olólùfẹ́ èdè Yorùbá, ẹ gbádùn ẹ kí ẹ tó sùn 

Àlọ́ oo
Àlọ̀ 
Àlọ́ yí dá fìrìgbagbo, ó dá lórí ọmọbìnrin Alaáìgbọ́ràn

Ni ayé àtijó,ọmọbìnrin kan wà ní ìlú kan. Ọmọbìnrin yìí rẹwà bí egbin. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin ni ó fé fi s'aya ṣùgbọ́n kò gbà fún ẹnì kankan nínú wọn. Àwọn òbí rẹ ni yan ọkọ fún ṣùgbọ́n kò tẹ́lẹ̀ ẹniti wọn yan fún un.

Ní ọjọ́ kan ó ṣe alápàdé ọmọkùnrin kan tí ó rẹwà, ó sì wu ọmọbìnrin yìí dáadáa. Ó sọ fún ọmọkùnrin yìí pé òun nífẹ̀ẹ́ rẹ, òun sì fẹ́ kí ó jé ọkọ òun. Ọmọkùnrin yìí kọ̀ pé òun kò ní fẹ́ ọmọbìnrin yìí, ṣùgbọ́n ó fàáké kọ́rí pé ọmọkùnrin yìí ni òun ni láti fẹ́ láìmọ̀ pé sènìyàn-sẹranko ni ọkùnrin náà, erè inú omi ni, ó paradà láti wá sí ìjọ àwọn adáríhunrun lásán ni. Nígbà tí ọmọbìnrin yìí kò gbà, ni ọmọkùnrin yìí bá sọ pé òun yóò fẹ́ẹ, ó sì sọ fún ọmọbìnrin náà wí pé ilé òun jìnà,ọmọbìnrin sọ fún un pé ibikíbi tí ọmọkùnrin yìí bá ń lọ òun yóò bàa lọ. 



Nígbà tí wọ́n rìn díè tí wọ́n dé ibi tí àwọ̀ ọmọkùnrin yìí wà, ní ọmọkùnrin yìí bá yà sí inú igbó tí ó sì gbé àwọ̀ erè rẹ̀ wọ̀. Bí erè ti fà dé ojú ọ̀nà ni ó fa Ẹsẹ̀ ọmọbìnrin yìí ṣe rí ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ yìí ni ó bá f'ariwo ta pẹ̀lú orin lẹ́nu báyìí pé :

#Ọmọbìnrin: - - - - - - - - - -Nìkún o, Nìkún ninì
#Ègbè: - - - - - - - - - - Ninini, Nìkún ninì
#Ọmọbìnrin: - - - - - - - - - - - Nìkún o, Nìkún ninì
#Ègbè: - - - - - - - - - - - Ninini, Nìkún ninì
#Ọmọbìnrin: - - - - - - - - - - --bàbá fi mí f'ọkọ ẹ̀mí ò gbọ́ o
#Ègbè: - - - - - - - - - - Ninini, Nìkún ninì
#Ọmọbìnrin: - - - - - - - - - - ìyá fi mí f'ọkọ ẹ̀mí ò gbà o
#Ègbè: - - - - - - - - - - Ninini, Nìkún ninì
#Ọmọbìnrin: - - - - - - -ọkọ nìkan tí mo fẹ́ ló bá derè o
#Ègbè: - - - - - - - - Ninini, Nìkún ninì
#Ọmọbìnrin: - - - - - - Nìkún o, Nìkún ninì
#Ègbè: - - - - - - - - Ninini, Nìkún ninì

Bí ọmọbìnrin yìí ṣe ń kọ orin ni erè bẹ̀rẹ̀ sí gbéemi díè díẹ̀. Ṣé orí tí yóò sunwọ̀n nigb'aláwò re ko ni, ọkàn nínú àwọn ọmọkùnrin tí wọ́n tí k'ọnu sí obìnrin yìí láti fi s'aya wà lórí ẹ̀gùn tí ó ń s'ọdẹ. Bí ó ti gbé ojú wo iwájú ni ó rí erè tí ó ń gbé ọmọbìnrin yìí mì. Bí ọkùnrin yìí ṣe ta ìbọn mọ́ erè nìyí tí erè sí kú lẹ́yìn èyí ni ọmọbìnrin náà yọ jáde l'ẹnu erè.

Ìdí àlọ́ yìí ni pé kò yẹ kí á máa ṣe àìgbọràn sí àṣẹ àwọn òbí wa. Kí á sì tún má máa ṣe fáàri àṣejù.

Mo lérò wípé ẹ rí ẹ̀kọ́ kan tàbí méjì kọ́...

Ẹsẹ́ púpọ̀


Saturday 4 March 2017

Aṣọ ńlá kọ́ l'èèyàn ńlá

Gbogbo Onífújà kọ́ l'Ọmọlúàbí,
Gbogbo ènìyàn tí ẹ rí nínú ọkọ̀ aláfẹ́ kọ́ ni wọ́n n sojúse wọn lọ́dẹ̀dẹ̀,
Kìí se gbogbo ẹni tó wọsọ ìgbà ni ènìyàn iyì,
Gbogbo sànmọ̀nrí kó lèèyàn nlá,
Kìí kúkú se gbogbo arẹwà ló níwà,
Èrò kò kúkú mọkọ̀,
Tóbá dára láwọ̀,
só dára dénú irin?
Fàwọ̀rajà gbàlú gbàdúgbò kan,
Gbogbo ẹni tó wọsọ nlá kọ́ ni ènìyàn nlá,
Dẹ̀ngẹ́ tutù lẹ́hìn gbóná nínú,
Gbogbo ohun tó n dán kọ́ni wúrà,
Ọ̀pẹ ọ̀yìnbó fi dídùn sẹwà tí oró inú rẹ̀ lé lérínwó,
Ẹ jẹ́ ká sọ́ra fún ìtànjẹ àwọn alásọdùn,
Gbogbo ológe wúwo kọ́ lèèyan iyì,
Nitóri orí burúkú kìí wú túúlú,
A kìí dá ẹsẹ̀ asiwèrè mọ̀ lọ́nà,
A kìí morí olóyè láwùjọ.

Ẹjẹ́ ká sọ́ra fún àwọn Fàwọ̀rajà, kí a sì má fojú di ẹnikẹ́ni láwùjọ..

#EdeYorubaRewa


Thursday 23 February 2017

obìnrin kan àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́ta.

Àlọ́ míràn fún ìgbádùn gbogbo olólùfẹ́ èdè Yorùbá....
Àlọ́ oo
Àlọ̀ ọ ọ
Àlọ́ yí dá fìrìgbagbo, ó dá lórí obìnrin kan àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́ta.
Ni ìlú kan orúkọ ìlú náà ni olówó, obìnrin kan wà tí ó bí ọmọ mẹ́ta. Orúkọ àwọn ọmọ náà ni, #Wẹ́rẹ́wẹ́rẹ́ laá ṣẹ́gi, #Wàràwàrà làá wọ̀gbẹ́ àti #Ọmọniyun tí ó jẹ́ àbígbèyìn. Obìnrin yìí wá fẹ́ràn Ọmọniyun ju àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ, kò sì fi ìfẹ́ yìí pamọ́ fún àwọn ẹ̀gbọ́n Ọmọniyun.
Nígbà tí ó di ọjọ́ kan, àwọn ọmọ mẹ́tẹ́ẹ́ta jáde nílé, wọn kò sì mọ ọ̀nà ilé mọ́. Obìnrin yìí wá àwọn ọmọ rẹ̀ títí kò rí wọn. Nígbà tí ó ṣe, obìnrin yìí bẹ̀rẹ̀ sí wá àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú orin àti omijé lójú. Obìnrin náà bẹ̀rẹ̀ sí kọ orin báyìí pé:
Obìnrin             Èrò ọjà olówó
Agberin            JàlòlòJàlòlò
Obìnrin             Taa ló bá mi rọ́mọ mi,
Agberin            JàlòlòJàlòlò, Kíni orúkọ t'ọ́mọ rẹ máa ń jẹ? JàlòlòJàlòlò
Obìnrin             Ọ̀kan Wẹ́rẹ́wẹ́rẹ́ laá ṣẹ́gi
Agberin            JàlòlòJàlòlò
Obìnrin             Ọ̀kan Wàràwàrà làá wọ̀gbẹ́
Agberin            JàlòlòJàlòlò
Obìnrin            Ọ̀kan Ọmọniyun kékeré, ọ̀rọ̀ Ọmọniyun ló dùn mí jọjọ
Agberin           JàlòlòJàlòlò
Obìnrin           Èrò ọjà olówó
Agberin          JàlòlòJàlòlò
Bí ó ṣe ń kọ orin yìí, obìnrin yìí kò mọ̀ pé Wọ́n tí gbé àwọn ọmọ òun pamọ́ fẹ́ fi dá obìnrin yìí lára wípé kò yẹ kí á máa fẹ́ràn ọmọ kan ju èkejì lọ nítorí Olódùmarè ló fi àwọn ọmọ yìí ta wá lọ́re.
Obìnrin yìí tún bẹ̀rẹ̀ orin bí tí ìṣáájú. Nígbà tí ó ṣe, wọ́n taari méjì nínú àwọn ọmọ obìnrin yìí síta. Inú obìnrin yìí kò dùn torí pé kò rí Ọmọniyun tííṣe àbígbèyìn ọmọ rẹ̀. Àwọn ènìyàn sì gbìmọ̀ pọ̀ láti dá obìnrin yìí lójú. Ohun tí wọ́n sì ṣe ní wípé wọ́n pa Ọmọniyun wọn sọ sí obìnrin yìí. Bí obìnrin yìí tí ríi ni ó bú sí ẹkùn ni ó tún bẹ̀rẹ̀ sí kọ orin. Kò pẹ́ ni wọn ju òkùtù Ọmọniyun sí ìyá rẹ̀. Inú ìyá Ọmọniyun bàjé gidigidi, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí sunkún lọ sí ilé.
Àlọ́ yìí kọ́ wa wípé kí á máa fẹ́ràn ọmọ kan ju ọmọ èkejì lọ torí a kò mọ irú ohun tí àwọn ọmọ yìí leè dà ní ọjọ́ ọ̀la. Òkúta tí ọ̀mọ̀lé kọ̀ tún lè padà wá di igun ilé ni ọjọ́ ọ̀la.

Tuesday 21 February 2017

Ilé ayé ilé asán

Ilé ayé!
Ilé asán!
Àfọwọ́bàfiílẹ̀,
Ìmúlẹ̀mófo, Ayé ọ̀hún tí kò tó pọ́n,
A bùú, kò kúnwọ́,
A dàá sílẹ̀, kò seé sà,
Gbogbo ẹ̀ gbògbò ẹ̀, ẹsẹ̀ mẹfa,
Kò sí ohun táa mú wá sáyé,
Kò sì ní sí ohun táá mú lọ,
Gbogbo olówó ayé ń kú gbogbo ilé, ọkọ̀, àti ohun mèremère wọn kò ba rọrùn,
Mélòó ni gbogbo ara wa níwájú ikú?
Ẹ jẹ́ ká gbáyé se rere,
Nítorí ọjọ́ àtisùn ẹni,
Kò sí ohun táa se láyé tó gbé,
Oògùn àsegbé kan kò sí láyé níbi,
Àsepamọ́ ló wà,
Ilé ayé á kúkú tán,
Èwo làá n wayé máyà fún,
Ikú ni yóò gbẹ̀yin oníkálukú wa,
Ohun tí á tán làá pè ní Ayé,
Ẹ jẹ́ ká hùwà tó máa kuni kù ní sààréè,
Ẹ má jẹ̀ẹ́ kẹ́tàn ayé tàn wá mọ́,
Ọba òkè ni ẹ jẹ́ ká rọ̀ mọ́,
Òun ló leeè là wa,
Asán lórí asán layé yìí.
Mo sọ̀ yìí mo dúró náà.

#EdeYorubaRewa

Olúrómbí and Olúwéré

Fún ìgbádùn gbogbo olólùfẹ́ ojú ìwé yìí. Mo lérò wípé ẹ gbádùn ẹ dáradára.

Àlọ́ oo ,
Àlọ́ ọọ,
Àlọ́ yìí dá lórí #Olúrómbí àti #Olúwéré 




Ní ayé àtijó, obìnrin kan wà tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúrómbí. Obìnrin yìí kò sì fi inú soyún, bẹ́ẹ̀ ni kò fẹ̀yin gbọ́mọ pọ̀n, èyí jásí pé ó yàgàn. Ó wá ọmọ títí ṣùgbọ́n pàbó ló ń já sí. Dípò kí ó dúró de iṣẹ́ Olódùmarè, ó gba ọ̀dọ̀ olúwéré lọ. Ó ṣe eléyìí nígbà tí ó rí àwọn tí wọ́n jọ wà nínú ipò báyìí tí wọ́n ń gbọ́mọ pọ̀n. Olúrómbí gbéra ó lọ sí ọ̀dọ̀ olúwéré. Pẹ̀lú ìtara ni Olúrómbí fi jẹ́ ẹ̀jẹ́ pé bí olúwéré bá fún òun lómọ, òun yíò sì fún un ní ọmọ náà. Ẹ̀jẹ́ yìí jẹ́ ọ̀tun nítorí pé, ewúrẹ́ àgùntàn ni àwọn obìnrin ń padà wá fún olúwéré gẹ́gẹ́ bí ẹ̀jẹ́.

Lóòótọ́, Olúrómbí lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan tí ó sọ orúkọ rẹ̀ ní #Apọ́nbiepo. Apọ́nbiepo ń dàgbà, ìyá rẹ̀ kò sì rántí ẹ̀jẹ́ tí ó bá olúwéré dá.

Nígbà tí olúwéré retí Olúrómbí kí ó wá mú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ṣe tí kò ríi ni òun gan-an bá gbéra ni ọjọ́ kan ó gba ilé Olúrómbí lọ. Bí ó ṣe dé'bẹ̀ tí ó f'ojú kan Apọ́nbiepo ni ó bá lé lọ́wọ́ mú tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí mú lọ. Ọmọ yìí bẹ̀rẹ̀ si sunkún títí tí ìyá rẹ̀ Olúrómbí bẹ̀rẹ̀ sí sáré tẹ́lẹ̀ olúwéré títí olúwéré fi padà wọ inú igi lọ pẹ̀lú Apọ́nbiepo.

Olúrómbí bẹ̀rẹ̀ si bẹ olúwéré pẹ̀lú omijé lójú, ṣùgbọ́n dípò kí olúwéré dá ọmọ padà, orin ni ó bẹ̀rẹ̀ sí fi dáa lóhùn báyìí pé :

Olúwéré                  oníkálukú ń jẹ̀jẹ́ ewúrẹ́,
                               Ewúré ewúrẹ́,
                               oníkálukú ń jẹ̀jẹ́ àgùntàn,
                                Àgùntàn bọ̀lọ̀jọ̀,
                               Olúrómbí ń jẹ̀jẹ́ ọmọ rẹ̀,
                               ọmọ rẹ Apọ́nbiepo            
                               Olúrómbí oo 
#Agbeorin              janin-janin, ìrókò janin-janin

Olúwéré :              Olúrómbí oo
Agbeorin               janin-janin, ìrókò janin-janin

Báyìí ni Olúrómbí ṣe pàdánù ọmọ rẹ̀.

Ẹ̀kọ́ tí Àlọ́ yìí kọ́ wa wípé bí a bá jẹ́jẹ̀ẹ́ kí á rí wí pé ẹ̀jẹ́ tí a lè san ni a jẹ́, kí á má máa fi ìwànwara jẹ́ ẹ̀jẹ́. Ní èkejì ó yẹ kí á máa kó gbogbo àníyàn wà tí Olódùmarè. Kí á má máa fi ìwànwara wá nǹkan torí ọba ọ̀kẹ́ t'óṣe fún Táyé kò gbàgbé Kẹ́hìndé, ẹ jẹ́ kí á sọ́ra.

#EdeYorubaRewa

Sunday 5 February 2017

Àforítì lebọ

Àforítì lebọ 

Àforítì lebọ, Òtítọ́ nii o, 
Bẹ́ẹ̀ náà ló rí, 
Kòsí bí omi se lè rú tó, 
ibi kí ó tòrò ni á jásí,
Adìẹ tí ò kú leè j'àgbàdo,
Ìyà tí n jẹ ọmọ fún ogún ọdún,
Òsì tí ń ta ọmọ fún ọgbọ́n oṣù,
Bí ọmọ náà bá leè ní àforítì,
Adùn náà ni gbẹ̀yìn irú wọn,
Ìyà tí n jẹ àwọ̀sùn ológbò kò mọ níwọ̀n, tóbá dàgbà tán, níí bọ́ lọ́wọ́ Ìyà,
Akẹ́kọ̀ọ́ tó ní àforítì, áá ní àṣeyọrí,
Ọmọ isẹ́ tó ní àforítì, áá di ọ̀gá,
Àforítì làkọ́kọ́,
Akíkanjú labí tẹ̀le ẹ,
Ìwà ìrẹ̀lẹ̀ lọmọ ikẹhin,
Ẹni tó bá ní mẹ́tẹ̀ẹ̀ta lamọ̀ léèyàn.
Àforítì lérè púpọ̀,
Ẹjẹ́ kí gbogbo wa ni Ìforítì.....

Èmi Semiat Olufunke Aya Tiamiyu sòyí mo dúró ná oooo

#Akúìmúraọ̀sẹ̀tuntun

#EdeYorubaRewa