Tuesday 11 July 2017

Ọ̀RỌ̀ Ìkìlọ̀

Ohun tá a ṣe ní kọ̀kọ̀
Táa fẹ́ ká ráyè mọ̀ nípa ẹ̀
Ohun tó dára ní,
Èyí táa ṣe ní kọ̀rọ̀
Táà fẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó rí
Ohun burúkú ni
Ṣùgbọ́n bó ò tafà sókè, tó o yídò borí
Bí ọba ayé ò rí ọ, tọ̀run ń wò ọ́
Ìwọ máa gbọ̀nà ẹ̀bùrú
Sọmọ ádámọ lọ́sẹ́
Lójú ilé ni elédùmarè ó gbà mú ọ
Ìwọ tó o ní kú lọ́wọ́
Tó o látaare
Ìwọ tó jẹ́ kìkì ìkà
Tó jẹ́ pẹ́nu to bá kàn ọ o kàn ìjàngbọ̀n
Máa ṣe nìṣó, ẹ̀san ń bọ̀
Rántí pé, ìwà tó o bá hu
Lọmọ máa débá
Ẹni tó gbèbù ìkà ọmọ rẹ yíò je àjeyó ìyà
Yíò je ajẹsẹ́kù dọmọ ọmọ
Ẹ jẹ́ ká gbélé ayé ṣe rere
Ká lè ní gbẹ̀yìn tó dùn.
Kò sí ohun tá a ṣe tí elédùmarè ò rí
Ẹ jẹ ṣe dára ní gbogbo ibikíbi tí a bá wà.



#EdeYorubaRewa

No comments:

Post a Comment