ỌBA LÓ LADE. ÌJÒYÈ NÁÀ LÓ NI ILEKE. ITAN NTE SÍWÁJÚ.
ÀKỌLÉ ITAN: ṢỌ ẸRÚ KO
APÁ KEJÌ
Ibẹru bojo tí bàa gbogbo ara ilu ẹlẹgan, ṣe ogún ó dàbí ẹni ń jiyan, bẹ́ẹ̀ ni ó dàbí ẹni ń jẹka.
Are ni ajanimogun nilu ẹlẹgan,ọdẹ ni àmọ́ ọdẹ tí rẹ kì npa ẹkùn bẹ́ẹ̀ ni kí npa àgbọ̀nrín. Ọdẹ etile ló ńṣe bí kò pá Ọya, kò pá emo, kò sì de isa okete. Nígbà tó kú ọjọ marun kí àsìkò tí ìlú tẹrẹ dá fún ìlú ẹlẹgan pé, ajanimogun gbéra lọ bá àwọn ilumoye pé tí wọ́n bá lè gbà òun láyé, òun ṣetan láti lewaju ogún fún wọn, ó sì dájú pé ajaye ni òun yóò jagun náà.
Tika tẹgbìn ni àwọn olóyè wo ajanimogun, wọn ní bóyá ni nkan ó ti tà sì lọpọlọ. Abi báwo ni ọdẹ tí npa ẹmọ, Pa afé ṣe fẹ lọ koju ogún, oogun wo loni tí yóò fi jagun ọhun ni ajaye? Àbí torí kí ajanimogun lè d'oba ló ṣe ni òun fẹ lọ dojú kọ ogún?? Gbogbo ìbéèrè yìí ni àwọn olóyè nro lọ́kàn ara wọn,àmọ́ kò ye wọn.
Wọn ní kí ajanimogun sì máa lọ náà pé tí yóò bá fi di ọjọ́ kejì, àwọn yóò ti mọ̀ ibi tí àwọn yóò bá ìyára ja lórí ọrọ náà.
Lẹ́yìn tí ajanimogun kúrò lọdọ àwọn olóyè, iyalode ni kí wọ́n jẹ́ káwọn gba ajanimogun láàyè láti lọ jagun, bóyá eledua lè gbé ògo fún ọlẹ rẹ. To bá sì ṣe bẹ́ẹ̀ bá ogún lọ, a jẹ pe ohun ojú nwa lójú nri. Àwọn olóyè tó kú fara mọ èrò iyalode, wọn si pinnu láti tẹle aba rẹ.
Ní òwúrọ ọjọ kejì àwọn olóyè rán onise sì ajanimogun pé ìlú tí fara mọ èrò rẹ, wọn si ti gba pe ko lọ dojú kọ ogún fún wọn. Wọn súre fún pé yóò lọ rẹ, yóò sì bo rè. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún fi ikilọ ati àdéhùn tí ọ̀rọ̀ wọ́n lẹ́yìn. Wọn ní bí ajanimogun bá kọ láti ṣẹ́gun pípa ni ilu yóò pá òun àti gbogbo ẹbi rẹ run,àmọ́ bí ó bá lè já ogún náà ni ajaye, àwọn yóò fi jọba ìlú ẹlẹgan tuntun.....
ṢE AJANIMOGUN YÓÒ ṢÍ LỌ SOJU OGUN PẸ̀LÚ ALAKALE TI ÌLÚ GBÉ SI NÍWÁJÚ BÁYÌÍ????
ITAN Ń TẸ ṢÍWÁJÚ
Ẹ fojú sọ́nà fún apá kẹta
Láti ọwọ́ Ọ̀gbẹ́ni Aremo Jah-Akewi
www.facebook.com/EdeYorubaRewa
#EdeYorubaRewa
Sunday, 7 January 2018
Thursday, 4 January 2018
Àkọlé ìtàn : ṢO ẸRÚ KO
ÀTI SE ÈÉ, Ó TI JINÀ.
Àkọlé ìtàn : ṢO ẸRÚ KO
APÁ KÌÍNÍ
Ojúmọ́ tí n mo, ooye tí bẹ̀rẹ̀ si ni là, ó ti ń bọ̀ sọ wo afemoju. Àwọn aráàlú elegan tí ń gbéra nílé láti gba ẹnu ìṣe wọn lọ, ṣe ìdí isẹ ẹni là tí ń mọni lole.
Bi àwọn èèyàn ti ń jí ni wọn bẹ̀rẹ̀ si ni gbo tí kowe nke labaadi. Bí ojúmọ́ ṣe ń mọ sì bẹẹ nígbè ẹyẹ yìí túbọ̀ n pọ sì. Ara bẹ̀rẹ̀ si fú àwọn aráàlú ohun lè mú kí kowe máa ké lafemoju. Se kowe ó kúkú nke lásán, ó ní láti jẹ pe ohun burúkú kan tí ṣẹlẹ̀ sí lu elegan ni.
Nígbà tí yóò fi di ÒWÚRỌ̀ kukutu, ní alago ọba bẹ̀rẹ̀ si ni lu aago, kaluku ń jáde wá gbọ ìṣe tí alaago náà fẹ jẹ́. Òfò ńlá tí ṣe ìlú elegan, àkùkọ tí kò lẹyin ọmọkùnrin alágbára. Alago jabo fún gbogbo ìlú pé kabiyesi àwọn, tí ńṣe ọba ọlọbẹ tí ìlú ẹlẹ́gan tí waja lóru mójú. Tori náà isede yóò wà fún odindi ọjọ méje láti ṣe oro fún ìsìnkú ọba. Gbogbo ìlú kan gogo nítorí ìròyìn láabi tí wọn gbo.
Àwọn ilumoye ṣeto bí wọn yóò ṣe fi ilẹ bo àṣírí òkú ọba, bí irun ti ń bo àṣírí orí.
Àdánù ńlá gbaa ni ikú ọba ọlọbẹ jẹ́ fún gbogbo ìlú ẹlẹ́gan pátápátá. Ìgbà ìṣàkóso rẹ tú t'onile t'alejo lára, eku nke bí eku, ẹyẹ nke bí ẹyẹ bẹẹ lọmọ ènìyàn ń fohùn bí èèyàn, amo ikú ṣe ká bo se fi ọba ọlọbẹ là gbogbo ìlú ẹlẹ́gan lójú.
Lẹyin oṣù kan tí ọba ọlọbẹ tí waja ni ilu tẹrẹ ranse ogún sì wọn, ṣe fami nfa ọ kúkú ti wá laarin ọba ìlú tẹrẹ yìí pẹlu ọba ọlọbẹ kò tó di pé ó waja. Èrò àwọn ilumoye tẹ́lẹ̀ ni pé bóyá ìlú tẹrẹ yóò jáwọ lórí ọ̀rọ̀ náà nígbà tí ọba ọlọbẹ tí waja, àmọ́ ibi tí wọ́n fojú sì ọ̀nà ó gbà ìbè, ó jọ bí ẹni pé ọrọ ti fẹ́ bá ẹyin yọ.
Ọ̀sẹ̀ mẹta péré ni ilu tẹrẹ fún ìlú ẹlẹ́gan láti lọ múra ogún silẹ, torí ìjà nbo kànnàkànnà ṣe tàn tó fẹ́ bo ẹyẹ ẹga. Àwọn ilumoye ṣètò pé kí àwọn ìdílé tó njẹ ọba fà ọmọ oyè silẹ, kí wọn lé yàn ọba èyí tí yóò lewaju ogún tó nbo lọ́nà. Àmọ́ kò sẹni tó yọjú.
Ọ̀pọ̀ lo wù kó joyè, àmọ́ aile fara ẹni jin ó jẹ ki ẹnikẹ́ni yọjú láti gorí apere bàbà rẹ. Mo ńbọ
ìtàn wá láti ọ̀dọ̀ Ọ̀gbẹ́ni Aremo Jah-Akewi
Ẹ fojú sọ́nà fún apá kejì.
www.facebook.com/EdeYorubaRewa
#EdeYorubaRewa
Àkọlé ìtàn : ṢO ẸRÚ KO
APÁ KÌÍNÍ
Ojúmọ́ tí n mo, ooye tí bẹ̀rẹ̀ si ni là, ó ti ń bọ̀ sọ wo afemoju. Àwọn aráàlú elegan tí ń gbéra nílé láti gba ẹnu ìṣe wọn lọ, ṣe ìdí isẹ ẹni là tí ń mọni lole.
Bi àwọn èèyàn ti ń jí ni wọn bẹ̀rẹ̀ si ni gbo tí kowe nke labaadi. Bí ojúmọ́ ṣe ń mọ sì bẹẹ nígbè ẹyẹ yìí túbọ̀ n pọ sì. Ara bẹ̀rẹ̀ si fú àwọn aráàlú ohun lè mú kí kowe máa ké lafemoju. Se kowe ó kúkú nke lásán, ó ní láti jẹ pe ohun burúkú kan tí ṣẹlẹ̀ sí lu elegan ni.
Nígbà tí yóò fi di ÒWÚRỌ̀ kukutu, ní alago ọba bẹ̀rẹ̀ si ni lu aago, kaluku ń jáde wá gbọ ìṣe tí alaago náà fẹ jẹ́. Òfò ńlá tí ṣe ìlú elegan, àkùkọ tí kò lẹyin ọmọkùnrin alágbára. Alago jabo fún gbogbo ìlú pé kabiyesi àwọn, tí ńṣe ọba ọlọbẹ tí ìlú ẹlẹ́gan tí waja lóru mójú. Tori náà isede yóò wà fún odindi ọjọ méje láti ṣe oro fún ìsìnkú ọba. Gbogbo ìlú kan gogo nítorí ìròyìn láabi tí wọn gbo.
Àwọn ilumoye ṣeto bí wọn yóò ṣe fi ilẹ bo àṣírí òkú ọba, bí irun ti ń bo àṣírí orí.
Àdánù ńlá gbaa ni ikú ọba ọlọbẹ jẹ́ fún gbogbo ìlú ẹlẹ́gan pátápátá. Ìgbà ìṣàkóso rẹ tú t'onile t'alejo lára, eku nke bí eku, ẹyẹ nke bí ẹyẹ bẹẹ lọmọ ènìyàn ń fohùn bí èèyàn, amo ikú ṣe ká bo se fi ọba ọlọbẹ là gbogbo ìlú ẹlẹ́gan lójú.
Lẹyin oṣù kan tí ọba ọlọbẹ tí waja ni ilu tẹrẹ ranse ogún sì wọn, ṣe fami nfa ọ kúkú ti wá laarin ọba ìlú tẹrẹ yìí pẹlu ọba ọlọbẹ kò tó di pé ó waja. Èrò àwọn ilumoye tẹ́lẹ̀ ni pé bóyá ìlú tẹrẹ yóò jáwọ lórí ọ̀rọ̀ náà nígbà tí ọba ọlọbẹ tí waja, àmọ́ ibi tí wọ́n fojú sì ọ̀nà ó gbà ìbè, ó jọ bí ẹni pé ọrọ ti fẹ́ bá ẹyin yọ.
Ọ̀sẹ̀ mẹta péré ni ilu tẹrẹ fún ìlú ẹlẹ́gan láti lọ múra ogún silẹ, torí ìjà nbo kànnàkànnà ṣe tàn tó fẹ́ bo ẹyẹ ẹga. Àwọn ilumoye ṣètò pé kí àwọn ìdílé tó njẹ ọba fà ọmọ oyè silẹ, kí wọn lé yàn ọba èyí tí yóò lewaju ogún tó nbo lọ́nà. Àmọ́ kò sẹni tó yọjú.
Ọ̀pọ̀ lo wù kó joyè, àmọ́ aile fara ẹni jin ó jẹ ki ẹnikẹ́ni yọjú láti gorí apere bàbà rẹ. Mo ńbọ
ìtàn wá láti ọ̀dọ̀ Ọ̀gbẹ́ni Aremo Jah-Akewi
Ẹ fojú sọ́nà fún apá kejì.
www.facebook.com/EdeYorubaRewa
#EdeYorubaRewa
Thursday, 14 September 2017
Ìjàpá àti ẹyẹ Àdàbà
Èyí ni Àlọ́ àpagbè fún gbogbo olólùfẹ́ ojú ìwé yìí, mọ lérò wípé ẹ ò gbádùn ẹ.
Àlọ́ oooo
Àlọ́ ọọọọ
Àlọ́ yìí dá lórí #ÌjàpáatiẹyẹÀdàbà
Gégé Bí ẹ̀yin náà ti mọ̀, alàgàbàgebè ni Ìjàpá, olè àti ọ̀kánjúwà ni pẹ̀lú. Ní ayé àtijó, Ìjàpá àti Ẹyẹ Àdàbà jọ ń ṣe ọ̀rẹ́. Àdàbà ni ẹṣin kan tí ó máa ń gùn kiri tí Ìjàpá kò sì ní nǹkankan. Ìjàpá ronú lọ́jọ́ kan, ó sì gbèrò bí yóò ti ṣe pa ẹṣin Àdàbà. Ó rí pé Àdàbà gbayì láàrin àwùjọ èyí tí kò dùn mọ̀ Ìjàpá nínú.
Nígbà tí ó di ọjọ́ kan Ìjàpá dá ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yín, ó pa ẹṣin Àdàbà. Àdàbà kò bínú sí kíkú tí ẹṣin rẹ̀ kú. Ohun tí ó ṣe ni pé ó gé orí ẹṣin náà ó bòó mọ́lẹ̀ ó wá fi ojú ẹṣin si ìta tí ènìyàn leè máa rí dáadáa. Bí Ìjàpá ti ń kọjá lọ ni ó rí ojú tí ó yọ síta. Eléyìí yàá lẹ́nu, kíá ó gbéra ó di ilé ọba. Nígbà tí ó dé ààfin, ó sọ fún ọba pé òun ti rí ibi tí ilé gbé lójú. Eléyìí ya ọba lẹ́nu, ó sì tún bí Ìjàpá bóyá ohun tí ó ń sọ dáa lójú. Ìjàpá sọ fún ọba pé ó dá òun lójú, ó sì tún wá fi dá ọba lójú pé bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ kí ọba pa òun. Nígbà yìí ni ọba pe gbogbo àwọn ìjòyè àti ẹmẹ̀wà rẹ̀ pé kí àwọn lọ wo ibi tí ilẹ̀ gbé lójú. Ìjàpá ni ó síwájú tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ orin báyìí pé;
Ìjàpá___________ Mo ti rí ibi ilẹ̀ gbé lójú
Agberin________ Ilẹ̀
Ìjàpá___________ Mo ti rí ibi ilẹ̀ gbé lójú
Agberin________ Ilẹ̀
Báyìí ni gbogbo wọn ń dá reirei lọ sí ibi tí ilẹ̀ gbé lójú. Bí Àdàbà ti gbọ́ ohun tí Ìjàpá ṣe yìí ni ó bá sáré lọ sí ibi tí ó bo orí ẹṣin rẹ̀ tí ó wó sí, ni ó bá wú orí náà kúrò lọ sí ibòmíràn. Nígbà tí ọba ìjòyè àti àwọn ẹmẹ̀wà dé ibi tí Ìjàpá wí, wọn kò rí nǹkan kan Ìjàpá bẹ̀rẹ̀ sí tú ilẹ̀ kiri títí kò rí ojú kankan. Ìgbà yí ni ọba bínú gidigidi pé Ìjàpá pa irú irọ́ tí ó tó báyìí àti pé ó tún da òun, àwọn ìjòyè àti àwọn ẹmẹ̀wà láàmú láti wá wo ohun tí kò sí níbẹ̀. Kíá ni ọba pàṣẹ pé kí wọn ó ti ojú Ìjàpá yọ'dà kí wọn ó ṣì ti ẹ̀yìn rẹ̀ kì í bọ àkọ̀.Eléyìí jásí pé wọn paá. Báyìí ni Ìjàpá fi ìlara pa ara rẹ̀.
#EdeYorubaRewa
Àlọ́ oooo
Àlọ́ ọọọọ
Àlọ́ yìí dá lórí #ÌjàpáatiẹyẹÀdàbà
Gégé Bí ẹ̀yin náà ti mọ̀, alàgàbàgebè ni Ìjàpá, olè àti ọ̀kánjúwà ni pẹ̀lú. Ní ayé àtijó, Ìjàpá àti Ẹyẹ Àdàbà jọ ń ṣe ọ̀rẹ́. Àdàbà ni ẹṣin kan tí ó máa ń gùn kiri tí Ìjàpá kò sì ní nǹkankan. Ìjàpá ronú lọ́jọ́ kan, ó sì gbèrò bí yóò ti ṣe pa ẹṣin Àdàbà. Ó rí pé Àdàbà gbayì láàrin àwùjọ èyí tí kò dùn mọ̀ Ìjàpá nínú.
Nígbà tí ó di ọjọ́ kan Ìjàpá dá ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yín, ó pa ẹṣin Àdàbà. Àdàbà kò bínú sí kíkú tí ẹṣin rẹ̀ kú. Ohun tí ó ṣe ni pé ó gé orí ẹṣin náà ó bòó mọ́lẹ̀ ó wá fi ojú ẹṣin si ìta tí ènìyàn leè máa rí dáadáa. Bí Ìjàpá ti ń kọjá lọ ni ó rí ojú tí ó yọ síta. Eléyìí yàá lẹ́nu, kíá ó gbéra ó di ilé ọba. Nígbà tí ó dé ààfin, ó sọ fún ọba pé òun ti rí ibi tí ilé gbé lójú. Eléyìí ya ọba lẹ́nu, ó sì tún bí Ìjàpá bóyá ohun tí ó ń sọ dáa lójú. Ìjàpá sọ fún ọba pé ó dá òun lójú, ó sì tún wá fi dá ọba lójú pé bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ kí ọba pa òun. Nígbà yìí ni ọba pe gbogbo àwọn ìjòyè àti ẹmẹ̀wà rẹ̀ pé kí àwọn lọ wo ibi tí ilẹ̀ gbé lójú. Ìjàpá ni ó síwájú tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ orin báyìí pé;
Ìjàpá___________ Mo ti rí ibi ilẹ̀ gbé lójú
Agberin________ Ilẹ̀
Ìjàpá___________ Mo ti rí ibi ilẹ̀ gbé lójú
Agberin________ Ilẹ̀
Báyìí ni gbogbo wọn ń dá reirei lọ sí ibi tí ilẹ̀ gbé lójú. Bí Àdàbà ti gbọ́ ohun tí Ìjàpá ṣe yìí ni ó bá sáré lọ sí ibi tí ó bo orí ẹṣin rẹ̀ tí ó wó sí, ni ó bá wú orí náà kúrò lọ sí ibòmíràn. Nígbà tí ọba ìjòyè àti àwọn ẹmẹ̀wà dé ibi tí Ìjàpá wí, wọn kò rí nǹkan kan Ìjàpá bẹ̀rẹ̀ sí tú ilẹ̀ kiri títí kò rí ojú kankan. Ìgbà yí ni ọba bínú gidigidi pé Ìjàpá pa irú irọ́ tí ó tó báyìí àti pé ó tún da òun, àwọn ìjòyè àti àwọn ẹmẹ̀wà láàmú láti wá wo ohun tí kò sí níbẹ̀. Kíá ni ọba pàṣẹ pé kí wọn ó ti ojú Ìjàpá yọ'dà kí wọn ó ṣì ti ẹ̀yìn rẹ̀ kì í bọ àkọ̀.Eléyìí jásí pé wọn paá. Báyìí ni Ìjàpá fi ìlara pa ara rẹ̀.
#EdeYorubaRewa
Àlọ́ àpagbè
Àlọ́ àpagbè míràn fún gbogbo olólùfẹ́ ojú ìwé yìí. Mo lérò wípé ẹ ò gbàdúrà e
Àlọ́ oooo
Àlọ́ ọọọọ
Àlọ́ yìí dá lórí #ẸkùnàtiIkùn
Ní ìlú àwọn ẹranko, kìnnìún ni Ọba wọn. Nígbà tí ó di ọjọ́ kan, Ọba ẹranko pe gbogbo àwọn ẹranko jọ, ó sọ fún wọn pé òun fẹ́ dá ọjọ́ tí àwọn ẹranko yóò wa ṣe eré fún òun. Ó sọ pé ẹni tí ó bá lu ìlù dáadáa òun yóò da lọ́lá. Nítorí ìdí èyí ó ní kí ẹranko kọ̀ọ̀kan lọ kan ìlù. Gbogbo àwọn ẹranko gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọba, wọ́n dárí lọ sí ilé wọn. Ẹni kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ẹranko ń gbìyànjú à ti kan ìlù. Ṣùgbọ́n dípò kí ẹranko kan tí orúkọ rẹ ń jẹ ikún ó kan ìlù tie, ní ṣe ni ó lọ gbé ìlú ẹkùn níbi tí ẹkùn gbé e sí. Ẹkùn bẹ̀rẹ̀ sí wa ìlú rẹ, ó wàá títí kò ri. Nígbà tí ó di ọjọ́ aré, ẹkùn jí ni kùtùkùtù ó lọ dúró ní ọ̀nà tí ó lọ sí ilé kìnnìún ọba ẹranko. Bí ẹranko kọ̀ọ̀kan bá ti fe kọjá ni ẹkún yóò yọ sí i tí yóò sì sọ pé kí ó lu ìlù rẹ̀ kí òun gbọ́. Orin ni ẹkún fi ń sọ eléyìí fún wọn tí orin náà sì lọ báyìí :
Ẹkùn________ Ríkíríkijàn
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ríkíríkijàn
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ aré
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ ayò
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Wọ́n ní á kànlù, mo kànlù
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Mo gbé ìlú mi s'àgbàlá
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọmọ ẹranko gbé e lọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Lùlù rẹ kí n gbọ́
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Lùlù rẹ kí n mọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakúkú rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakùkù rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ìlù mi kọ́ùn ni
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Rékọjá o máa lọ
Agberin_____Àríkijàn
Báyìí ni ẹranko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọjá tí ẹkùn sì ń kọ orin bákan náà. Nígbà tí ó kan ikùn láti kọjá, ẹ̀rù ti bẹ̀rẹ̀ sí bàa. Ẹkùn tún bẹ̀rẹ̀ orin rẹ̀ :
Ẹkùn________ Ríkíríkijàn
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ríkíríkijàn
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ aré
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ ayò
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Wọ́n ní á kànlù, mo kànlù
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Mo gbé ìlú mi s'àgbàlá
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọmọ ẹranko gbé e lọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Lùlù rẹ kí n gbọ́
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Lùlù rẹ kí n mọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakúkú rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakùkù rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ ìlù mi nùnun nì
Agberin_____ Àríkijàn
Bí ikùn tí gbọ́ pé ìlù ẹkùn ni òun gbé lọ́wọ́, pẹ̀ẹ̀ lójú ìlù sílè tí ó bẹ̀rẹ̀ sí sá lọ. Ẹkùn gbá tẹ́lẹ̀e,ṣùgbọ́n bí ẹkùn ṣe ni kí òun ó ki ikùn mọ́lẹ̀ ni ó ṣá wọ inú ihò lọ. Ikùn kò lọ láì f'arapa, èékánná ẹkùn ha ikùn ní ẹ̀gbẹ̀ méjèèjì. Bí ènìyàn bá rí ikùn lónìí, yóò rí pé ilà funfun wà ní ẹ̀gbẹ̀ méjèèjì ikùn di òní olónìí yìí o. Olè jíjà kò dára oooo
#EdeYorubaRewa
Àlọ́ oooo
Àlọ́ ọọọọ
Àlọ́ yìí dá lórí #ẸkùnàtiIkùn
Ní ìlú àwọn ẹranko, kìnnìún ni Ọba wọn. Nígbà tí ó di ọjọ́ kan, Ọba ẹranko pe gbogbo àwọn ẹranko jọ, ó sọ fún wọn pé òun fẹ́ dá ọjọ́ tí àwọn ẹranko yóò wa ṣe eré fún òun. Ó sọ pé ẹni tí ó bá lu ìlù dáadáa òun yóò da lọ́lá. Nítorí ìdí èyí ó ní kí ẹranko kọ̀ọ̀kan lọ kan ìlù. Gbogbo àwọn ẹranko gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọba, wọ́n dárí lọ sí ilé wọn. Ẹni kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ẹranko ń gbìyànjú à ti kan ìlù. Ṣùgbọ́n dípò kí ẹranko kan tí orúkọ rẹ ń jẹ ikún ó kan ìlù tie, ní ṣe ni ó lọ gbé ìlú ẹkùn níbi tí ẹkùn gbé e sí. Ẹkùn bẹ̀rẹ̀ sí wa ìlú rẹ, ó wàá títí kò ri. Nígbà tí ó di ọjọ́ aré, ẹkùn jí ni kùtùkùtù ó lọ dúró ní ọ̀nà tí ó lọ sí ilé kìnnìún ọba ẹranko. Bí ẹranko kọ̀ọ̀kan bá ti fe kọjá ni ẹkún yóò yọ sí i tí yóò sì sọ pé kí ó lu ìlù rẹ̀ kí òun gbọ́. Orin ni ẹkún fi ń sọ eléyìí fún wọn tí orin náà sì lọ báyìí :
Ẹkùn________ Ríkíríkijàn
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ríkíríkijàn
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ aré
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ ayò
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Wọ́n ní á kànlù, mo kànlù
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Mo gbé ìlú mi s'àgbàlá
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọmọ ẹranko gbé e lọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Lùlù rẹ kí n gbọ́
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Lùlù rẹ kí n mọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakúkú rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakùkù rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ìlù mi kọ́ùn ni
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Rékọjá o máa lọ
Agberin_____Àríkijàn
Báyìí ni ẹranko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọjá tí ẹkùn sì ń kọ orin bákan náà. Nígbà tí ó kan ikùn láti kọjá, ẹ̀rù ti bẹ̀rẹ̀ sí bàa. Ẹkùn tún bẹ̀rẹ̀ orin rẹ̀ :
Ẹkùn________ Ríkíríkijàn
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ríkíríkijàn
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ aré
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ ayò
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Wọ́n ní á kànlù, mo kànlù
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Mo gbé ìlú mi s'àgbàlá
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọmọ ẹranko gbé e lọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Lùlù rẹ kí n gbọ́
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Lùlù rẹ kí n mọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakúkú rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakùkù rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ ìlù mi nùnun nì
Agberin_____ Àríkijàn
Bí ikùn tí gbọ́ pé ìlù ẹkùn ni òun gbé lọ́wọ́, pẹ̀ẹ̀ lójú ìlù sílè tí ó bẹ̀rẹ̀ sí sá lọ. Ẹkùn gbá tẹ́lẹ̀e,ṣùgbọ́n bí ẹkùn ṣe ni kí òun ó ki ikùn mọ́lẹ̀ ni ó ṣá wọ inú ihò lọ. Ikùn kò lọ láì f'arapa, èékánná ẹkùn ha ikùn ní ẹ̀gbẹ̀ méjèèjì. Bí ènìyàn bá rí ikùn lónìí, yóò rí pé ilà funfun wà ní ẹ̀gbẹ̀ méjèèjì ikùn di òní olónìí yìí o. Olè jíjà kò dára oooo
#EdeYorubaRewa
Ọfọ̀ Ẹ̀fẹ̀
"Dúró ń bẹ̀"
Ohun tá a wí f'ọ́gbọ́
Lọ́gbọ́ ń gbọ́
Èyí tá a wí f'ọ́gbà
Lọgbà ń gbà
Inú ẹtù kìí dùn
Kó wálé ọdún
Inú àgbọ̀nrín kìí dùn
Kò wálé dìsẹ́nbà
Aṣọ ìbora kìí lápò
Kèké kìí ya ilé epo
Ìgbín kìí fẹ́yìn rìn
Ọ̀kadà kìí ní kọ̀ndọ́
Ijọ́ tí ọmọdé bá gbé'rà lóko
Ní dé ilé
Ijọ́ tókèlé ba dọ́nà ọ̀fun
Ní I de ikùn
Mo pàṣẹ fún ọ
Óyá!!! Fi àtẹ̀jíṣé yìí ránṣé
Ẹ̀fẹ̀ lèyí àbí àwàdà.
#EdeYorubaRewa
Ohun tá a wí f'ọ́gbọ́
Lọ́gbọ́ ń gbọ́
Èyí tá a wí f'ọ́gbà
Lọgbà ń gbà
Inú ẹtù kìí dùn
Kó wálé ọdún
Inú àgbọ̀nrín kìí dùn
Kò wálé dìsẹ́nbà
Aṣọ ìbora kìí lápò
Kèké kìí ya ilé epo
Ìgbín kìí fẹ́yìn rìn
Ọ̀kadà kìí ní kọ̀ndọ́
Ijọ́ tí ọmọdé bá gbé'rà lóko
Ní dé ilé
Ijọ́ tókèlé ba dọ́nà ọ̀fun
Ní I de ikùn
Mo pàṣẹ fún ọ
Óyá!!! Fi àtẹ̀jíṣé yìí ránṣé
Ẹ̀fẹ̀ lèyí àbí àwàdà.
#EdeYorubaRewa
Ọ̀RỌ̀ ìṣítí
Iṣu mi ọdún yìí
N kò ní fẹ́nìkan jẹ
Àgbàdo tí mo gbìn yìí
Kò ní kan ẹnìkan l'ẹ́nu
Ẹran ọ̀yà tí mo yìnbọn sí
Tíi mo ba ri
Emi nìkan ni yóò jẹ
Ko mọ̀ pé,
Ìgbẹ lẹran rẹ í gbé sí
Yorùbá bọ̀ wọ́n ní A kìí láhun ká nìyí
Ará ilé ahun ò gb'ádùn ahun
Ahun ọ̀hún
Ọ̀rọ̀ ìjìnlè Yorùbá lèyí
Ọmọ ahun, kò gbádùn ẹ
Ìyàwó ahun kò gbádùn ẹ
Gbogbo atótótu òkè yìí ń sàfihàn aburu
Tí ń bẹ nínú ahun ṣíṣe
Bó ṣe oúnjẹ lo ní, bó ṣe owó dákún ran aláìní lọ́wọ́
Àdáníkànje, ládánìkànku
Ẹni tó lawọ́
Kò tíì rí àánú Olódùmarè
Aánbọ̀sìbọ́sí ahun
Òkè lọ́wọ́ afúnni ń gbé
Ẹ jẹ ká jáwọ́ ahun ṣíṣe.
Ẹ má jee ká láhun nítorí ahun kò dára.
Bí ẹnikẹ́ni bá wá ìrànlọ́wọ́ dé ọ̀dọ̀ dákún gbìyànjú láti ràn wọ́n lọ́wọ́.
#EdeYorubaRewa.
N kò ní fẹ́nìkan jẹ
Àgbàdo tí mo gbìn yìí
Kò ní kan ẹnìkan l'ẹ́nu
Ẹran ọ̀yà tí mo yìnbọn sí
Tíi mo ba ri
Emi nìkan ni yóò jẹ
Ko mọ̀ pé,
Ìgbẹ lẹran rẹ í gbé sí
Yorùbá bọ̀ wọ́n ní A kìí láhun ká nìyí
Ará ilé ahun ò gb'ádùn ahun
Ahun ọ̀hún
Ọ̀rọ̀ ìjìnlè Yorùbá lèyí
Ọmọ ahun, kò gbádùn ẹ
Ìyàwó ahun kò gbádùn ẹ
Gbogbo atótótu òkè yìí ń sàfihàn aburu
Tí ń bẹ nínú ahun ṣíṣe
Bó ṣe oúnjẹ lo ní, bó ṣe owó dákún ran aláìní lọ́wọ́
Àdáníkànje, ládánìkànku
Ẹni tó lawọ́
Kò tíì rí àánú Olódùmarè
Aánbọ̀sìbọ́sí ahun
Òkè lọ́wọ́ afúnni ń gbé
Ẹ jẹ ká jáwọ́ ahun ṣíṣe.
Ẹ má jee ká láhun nítorí ahun kò dára.
Bí ẹnikẹ́ni bá wá ìrànlọ́wọ́ dé ọ̀dọ̀ dákún gbìyànjú láti ràn wọ́n lọ́wọ́.
#EdeYorubaRewa.
Tuesday, 22 August 2017
Ìkéde tí Ààrẹ Muhammad Buhari ṣe
Èyí ni ìkéde tí Ààrẹ Muhammad Buhari ṣe ní ọjọ́ kọkànlélógún, oṣù kẹjọ ọdún 2017 (21/08/2017).
Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà,
1) Mo dúpẹ́ fún Ọlọ́run àti gbogbo ọmọ orílè Nàìjíríà fún àdúrà yín, inú mi dùn láti padà sí orílè èdè Nàìjíríà tí mo tí jẹ Ààrẹ.
2) Dídúró mi ní orílè-èdè United Kingdom, gbogbo ohun tí ó ń lọ ní orílè èdè Nàìjíríà ni mo mọ. Àwọn ọmọ orílè èdè Nàìjíríà gbójú gbóyà láti sọ ohunkóhun, ṣùgbọ́n inú mi bàjé láti gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ mìíràn tí wọ́n ń sọ, pàápàá jù lọ lórí ẹ̀rọ ayélujára.
3) Ní ọdún 2003 lẹ́yìn ìgbátí mọ darapọ̀ mọ òṣèlú, Olóògbé olóyè Emeka Ojukwu wá sí ìlú mi ní Daura gẹ́gẹ́bí àlejò. A sọ̀rọ̀ ni kíkún nípa awon ìpèníjà tí orílè èdè Nàìjíríà ń dójú kọ fún ọjọ́ méjì tí Ilé sii sú báwa níbè. Àwa méjèèjì fi orí ọ̀rọ̀ wa kò wípé orílè èdè Nàìjíríà gbọdọ̀ wà ní Ìsòkan.
4) Ìsòkan orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ti ní ìyanjú kò sì ní ìdúnàdúrà nínú. Àko ní fi ààyè gba àwọn alaimokan láti dá wàhálà àti rògbòdìyàn sílè nítorí bí nkan bá bàjẹ́ tán, ńṣe ni wọn yíò sálọ tí wọn yíò sì jẹ́ kí ẹ̀jẹ̀ alaise ṣòfò.
5) Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó ní aàǹfààní láti gbé ayé àti láti lépa ohun rere tí wọ́n bá fẹ́ ṣe ni ibikíbi ni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láìsí ẹnì kankan tí yíò di wọn lọ́wọ́.
6) Mo nígbàgbọ́ wípé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó fi ara mọ́ èróngbà yìí.
7) Eléyìí kìí ṣe láti di àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti má mọ ohun tí ó kàn wón. Ṣùgbọ́n ẹwà àti ifamora orílẹ̀ èdè gbọdọ̀ fi àyè gba onírúurú ẹgbẹ́ láti ṣisẹ́ kí orílè èdè yìí le tẹsiwaju.
8) Àwọn ilé ìgbìmò Asòfin àti ilé ìgbìmò ní àwọn ìlú kọ̀ọ̀kan ni ẹ̀tọ́ láti gbìmọ̀ àti láti ṣe ìwádìí tí ó dára.
9) Ìlàkàkà àwọn ọmọ ilẹ̀ ìgbìmò náà ni wípé ó dára kí gbogbo wa máa gbé papọ ni ìrépọ̀ kí ó má sí ìpínyà láàrin wa.
10) Mo ń gbìyànjú láti má jẹ́ kí ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn bá àwọn elétò ààbọ̀ látàrí àṣeyọrí tí wọ́n tí ṣe ni ọdún kan àti oṣù díè sẹ́yìn.
11) Wọ́n gbọdọ̀ lé Ìgbé sùnmọ̀mí àti ìwà ọ̀daràn jìnà kí ó le fún gbogbo wa ni àǹfààní láti gbé ní ayọ̀ àti àlàáfíà.
12) Fún ìdí yìí a gbọdọ̀ tún ṣòkòtò wa ṣán làti gbé ogun tí àwọn wọ̀nyí:
Agbé sùmòmí Boko Haram
Àwọn gbọmọgbọmọ, àwọn Darandaran àti àgbẹ̀ àti
Èdè àiyedè láàrin wa pẹ̀lú iranlọwọ àwọn olóṣèlú. A gbọdọ̀ dojú kọ wón.
13) Gbogbo olólùfẹ́ orílè èdè Nàìjíríà, ìsisẹ́ papọ wa yíò jẹ́ kí á le gbé ogun tí àwọn ìpèníjà wọ̀nyí:
· Ètò ọrọ̀ ajẹ́
· Ìdàgbàsókè ètò òṣèlú àwa araawa
· Àti àlàáfíà tó yè kooro láàrin gbogbo ọmọ Nàìjíríà
14) Máa rí wípé gbogbo àwọn ìpèníjà yìí ni a borí wọn. Inú mi dùn láti padà sí orílè-èdè Nàìjíríà.
15) Ẹsẹ́ púpọ̀, Èdùmàrè a tún orílè èdè Nàìjíríà ṣe.
Àmín.
#EdeYorubaRewa
Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà,
1) Mo dúpẹ́ fún Ọlọ́run àti gbogbo ọmọ orílè Nàìjíríà fún àdúrà yín, inú mi dùn láti padà sí orílè èdè Nàìjíríà tí mo tí jẹ Ààrẹ.
2) Dídúró mi ní orílè-èdè United Kingdom, gbogbo ohun tí ó ń lọ ní orílè èdè Nàìjíríà ni mo mọ. Àwọn ọmọ orílè èdè Nàìjíríà gbójú gbóyà láti sọ ohunkóhun, ṣùgbọ́n inú mi bàjé láti gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ mìíràn tí wọ́n ń sọ, pàápàá jù lọ lórí ẹ̀rọ ayélujára.
3) Ní ọdún 2003 lẹ́yìn ìgbátí mọ darapọ̀ mọ òṣèlú, Olóògbé olóyè Emeka Ojukwu wá sí ìlú mi ní Daura gẹ́gẹ́bí àlejò. A sọ̀rọ̀ ni kíkún nípa awon ìpèníjà tí orílè èdè Nàìjíríà ń dójú kọ fún ọjọ́ méjì tí Ilé sii sú báwa níbè. Àwa méjèèjì fi orí ọ̀rọ̀ wa kò wípé orílè èdè Nàìjíríà gbọdọ̀ wà ní Ìsòkan.
4) Ìsòkan orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ti ní ìyanjú kò sì ní ìdúnàdúrà nínú. Àko ní fi ààyè gba àwọn alaimokan láti dá wàhálà àti rògbòdìyàn sílè nítorí bí nkan bá bàjẹ́ tán, ńṣe ni wọn yíò sálọ tí wọn yíò sì jẹ́ kí ẹ̀jẹ̀ alaise ṣòfò.
5) Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó ní aàǹfààní láti gbé ayé àti láti lépa ohun rere tí wọ́n bá fẹ́ ṣe ni ibikíbi ni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láìsí ẹnì kankan tí yíò di wọn lọ́wọ́.
6) Mo nígbàgbọ́ wípé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó fi ara mọ́ èróngbà yìí.
7) Eléyìí kìí ṣe láti di àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti má mọ ohun tí ó kàn wón. Ṣùgbọ́n ẹwà àti ifamora orílẹ̀ èdè gbọdọ̀ fi àyè gba onírúurú ẹgbẹ́ láti ṣisẹ́ kí orílè èdè yìí le tẹsiwaju.
8) Àwọn ilé ìgbìmò Asòfin àti ilé ìgbìmò ní àwọn ìlú kọ̀ọ̀kan ni ẹ̀tọ́ láti gbìmọ̀ àti láti ṣe ìwádìí tí ó dára.
9) Ìlàkàkà àwọn ọmọ ilẹ̀ ìgbìmò náà ni wípé ó dára kí gbogbo wa máa gbé papọ ni ìrépọ̀ kí ó má sí ìpínyà láàrin wa.
10) Mo ń gbìyànjú láti má jẹ́ kí ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn bá àwọn elétò ààbọ̀ látàrí àṣeyọrí tí wọ́n tí ṣe ni ọdún kan àti oṣù díè sẹ́yìn.
11) Wọ́n gbọdọ̀ lé Ìgbé sùnmọ̀mí àti ìwà ọ̀daràn jìnà kí ó le fún gbogbo wa ni àǹfààní láti gbé ní ayọ̀ àti àlàáfíà.
12) Fún ìdí yìí a gbọdọ̀ tún ṣòkòtò wa ṣán làti gbé ogun tí àwọn wọ̀nyí:
Agbé sùmòmí Boko Haram
Àwọn gbọmọgbọmọ, àwọn Darandaran àti àgbẹ̀ àti
Èdè àiyedè láàrin wa pẹ̀lú iranlọwọ àwọn olóṣèlú. A gbọdọ̀ dojú kọ wón.
13) Gbogbo olólùfẹ́ orílè èdè Nàìjíríà, ìsisẹ́ papọ wa yíò jẹ́ kí á le gbé ogun tí àwọn ìpèníjà wọ̀nyí:
· Ètò ọrọ̀ ajẹ́
· Ìdàgbàsókè ètò òṣèlú àwa araawa
· Àti àlàáfíà tó yè kooro láàrin gbogbo ọmọ Nàìjíríà
14) Máa rí wípé gbogbo àwọn ìpèníjà yìí ni a borí wọn. Inú mi dùn láti padà sí orílè-èdè Nàìjíríà.
15) Ẹsẹ́ púpọ̀, Èdùmàrè a tún orílè èdè Nàìjíríà ṣe.
Àmín.
#EdeYorubaRewa
Subscribe to:
Posts (Atom)






