Thursday, 14 September 2017

Àlọ́ àpagbè

Àlọ́ àpagbè míràn fún gbogbo olólùfẹ́ ojú ìwé yìí. Mo lérò wípé ẹ ò gbàdúrà e
Àlọ́ oooo
Àlọ́ ọọọọ
Àlọ́ yìí dá lórí #ẸkùnàtiIkùn

Ní ìlú àwọn ẹranko, kìnnìún ni Ọba wọn. Nígbà tí ó di ọjọ́ kan, Ọba ẹranko pe gbogbo àwọn ẹranko jọ, ó sọ fún wọn pé òun fẹ́ dá ọjọ́ tí àwọn ẹranko yóò wa ṣe eré fún òun. Ó sọ pé ẹni tí ó bá lu ìlù dáadáa òun yóò da lọ́lá. Nítorí ìdí èyí ó ní kí ẹranko kọ̀ọ̀kan lọ kan ìlù. Gbogbo àwọn ẹranko gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọba, wọ́n dárí lọ sí ilé wọn. Ẹni kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ẹranko ń gbìyànjú à ti kan ìlù. Ṣùgbọ́n dípò kí ẹranko kan tí orúkọ rẹ ń jẹ ikún ó kan ìlù tie, ní ṣe ni ó lọ gbé ìlú ẹkùn níbi tí ẹkùn gbé e sí. Ẹkùn bẹ̀rẹ̀ sí wa ìlú rẹ, ó wàá títí kò ri. Nígbà tí ó di ọjọ́ aré, ẹkùn jí ni kùtùkùtù ó lọ dúró ní ọ̀nà tí ó lọ sí ilé kìnnìún ọba ẹranko. Bí ẹranko kọ̀ọ̀kan bá ti fe kọjá ni ẹkún yóò yọ sí i tí yóò sì sọ pé kí ó lu ìlù rẹ̀ kí òun gbọ́. Orin ni ẹkún fi ń sọ eléyìí fún wọn tí orin náà sì lọ báyìí :

Ẹkùn________ Ríkíríkijàn
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ríkíríkijàn
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ aré
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ ayò
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Wọ́n ní á kànlù, mo kànlù
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Mo gbé ìlú mi s'àgbàlá
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọmọ ẹranko gbé e lọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Lùlù rẹ kí n gbọ́
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Lùlù rẹ kí n mọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakúkú rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakùkù rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ìlù mi kọ́ùn ni
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Rékọjá o máa lọ
Agberin_____Àríkijàn

Báyìí ni ẹranko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọjá tí ẹkùn sì ń kọ orin bákan náà. Nígbà tí ó kan ikùn láti kọjá, ẹ̀rù ti bẹ̀rẹ̀ sí bàa. Ẹkùn tún bẹ̀rẹ̀ orin rẹ̀ :

Ẹkùn________ Ríkíríkijàn
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________Ríkíríkijàn
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ aré
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọba ló dájọ́ ayò
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Wọ́n ní á kànlù, mo kànlù
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Mo gbé ìlú mi s'àgbàlá
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Ọmọ ẹranko gbé e lọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Lùlù rẹ kí n gbọ́
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________Lùlù rẹ kí n mọ
Agberin_____Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakúkú rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ Papakùkù rangbọndan
Agberin_____ Àríkijàn
Ẹkùn________ ìlù mi nùnun nì
Agberin_____ Àríkijàn

Bí ikùn tí gbọ́ pé ìlù ẹkùn ni òun gbé lọ́wọ́, pẹ̀ẹ̀ lójú ìlù sílè tí ó bẹ̀rẹ̀ sí sá lọ. Ẹkùn gbá tẹ́lẹ̀e,ṣùgbọ́n bí ẹkùn ṣe ni kí òun ó ki ikùn mọ́lẹ̀ ni ó ṣá wọ inú ihò lọ. Ikùn kò lọ láì f'arapa, èékánná ẹkùn ha ikùn ní ẹ̀gbẹ̀ méjèèjì. Bí ènìyàn bá rí ikùn lónìí, yóò rí pé ilà funfun wà ní ẹ̀gbẹ̀ méjèèjì ikùn di òní olónìí yìí o. Olè jíjà kò dára oooo

#EdeYorubaRewa

Ọfọ̀ Ẹ̀fẹ̀

"Dúró ń bẹ̀"
Ohun tá a wí f'ọ́gbọ́
Lọ́gbọ́ ń gbọ́
Èyí tá a wí f'ọ́gbà
Lọgbà ń gbà
Inú ẹtù kìí dùn
Kó wálé ọdún
Inú àgbọ̀nrín kìí dùn
Kò wálé dìsẹ́nbà
Aṣọ ìbora kìí lápò
Kèké kìí ya ilé epo
Ìgbín kìí fẹ́yìn rìn
Ọ̀kadà kìí ní kọ̀ndọ́
Ijọ́ tí ọmọdé bá gbé'rà lóko
Ní dé ilé
Ijọ́ tókèlé ba dọ́nà ọ̀fun
Ní I de ikùn
Mo pàṣẹ fún ọ
Óyá!!! Fi àtẹ̀jíṣé yìí ránṣé
Ẹ̀fẹ̀ lèyí àbí àwàdà.

#EdeYorubaRewa

Ọ̀RỌ̀ ìṣítí

Iṣu mi ọdún yìí
N kò ní fẹ́nìkan jẹ
Àgbàdo tí mo gbìn yìí
Kò ní kan ẹnìkan l'ẹ́nu
Ẹran ọ̀yà tí mo yìnbọn sí
Tíi mo ba ri
Emi nìkan ni yóò jẹ
Ko mọ̀ pé,
Ìgbẹ lẹran rẹ í gbé sí
Yorùbá bọ̀ wọ́n ní A kìí láhun ká nìyí
Ará ilé ahun ò gb'ádùn ahun
Ahun ọ̀hún
Ọ̀rọ̀ ìjìnlè Yorùbá lèyí
Ọmọ ahun, kò gbádùn ẹ
Ìyàwó ahun kò gbádùn ẹ
Gbogbo atótótu òkè yìí ń sàfihàn aburu
Tí ń bẹ nínú ahun ṣíṣe
Bó ṣe oúnjẹ lo ní, bó ṣe owó dákún ran aláìní lọ́wọ́
Àdáníkànje, ládánìkànku
Ẹni tó lawọ́
Kò tíì rí àánú Olódùmarè
Aánbọ̀sìbọ́sí ahun
Òkè lọ́wọ́ afúnni ń gbé
Ẹ jẹ ká jáwọ́ ahun ṣíṣe.
Ẹ má jee ká láhun nítorí ahun kò dára.
Bí ẹnikẹ́ni bá wá ìrànlọ́wọ́ dé ọ̀dọ̀ dákún gbìyànjú láti ràn wọ́n lọ́wọ́.

#EdeYorubaRewa.

Tuesday, 22 August 2017

Ìkéde tí Ààrẹ Muhammad Buhari ṣe

Èyí ni ìkéde tí Ààrẹ Muhammad Buhari ṣe ní ọjọ́ kọkànlélógún, oṣù kẹjọ ọdún 2017 (21/08/2017).

Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà,

1) Mo dúpẹ́ fún Ọlọ́run àti gbogbo ọmọ orílè Nàìjíríà fún àdúrà yín, inú mi dùn láti padà sí orílè èdè Nàìjíríà tí mo tí jẹ Ààrẹ.

2) Dídúró mi ní orílè-èdè United Kingdom, gbogbo ohun tí ó ń lọ ní orílè èdè Nàìjíríà ni mo mọ. Àwọn ọmọ orílè èdè Nàìjíríà gbójú gbóyà láti sọ ohunkóhun, ṣùgbọ́n inú mi bàjé láti gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ mìíràn tí wọ́n ń sọ, pàápàá jù lọ lórí ẹ̀rọ ayélujára.

3) Ní ọdún 2003 lẹ́yìn ìgbátí mọ darapọ̀ mọ òṣèlú, Olóògbé olóyè Emeka Ojukwu wá sí ìlú mi ní Daura gẹ́gẹ́bí àlejò. A sọ̀rọ̀ ni kíkún nípa awon ìpèníjà tí orílè èdè Nàìjíríà ń dójú kọ fún ọjọ́ méjì tí Ilé sii sú báwa níbè. Àwa méjèèjì fi orí ọ̀rọ̀ wa kò wípé orílè èdè Nàìjíríà gbọdọ̀ wà ní Ìsòkan.

4) Ìsòkan orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ti ní ìyanjú kò sì ní ìdúnàdúrà nínú. Àko ní fi ààyè gba àwọn alaimokan láti dá wàhálà àti rògbòdìyàn sílè nítorí bí nkan bá bàjẹ́ tán, ńṣe ni wọn yíò sálọ tí wọn yíò sì jẹ́ kí ẹ̀jẹ̀ alaise ṣòfò.

5) Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó ní aàǹfààní láti gbé ayé àti láti lépa ohun rere tí wọ́n bá fẹ́ ṣe ni ibikíbi ni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láìsí ẹnì kankan tí yíò di wọn lọ́wọ́.


6) Mo nígbàgbọ́ wípé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó fi ara mọ́ èróngbà yìí.

 7) Eléyìí kìí ṣe láti di àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti má mọ ohun tí ó kàn wón. Ṣùgbọ́n ẹwà àti ifamora orílẹ̀ èdè gbọdọ̀ fi àyè gba onírúurú ẹgbẹ́ láti ṣisẹ́ kí orílè èdè yìí le tẹsiwaju.

8) Àwọn ilé ìgbìmò Asòfin àti ilé ìgbìmò ní àwọn ìlú kọ̀ọ̀kan ni ẹ̀tọ́ láti  gbìmọ̀ àti láti ṣe ìwádìí tí ó dára.

9) Ìlàkàkà àwọn ọmọ ilẹ̀ ìgbìmò náà ni wípé ó dára kí gbogbo wa máa gbé papọ ni ìrépọ̀ kí ó má sí ìpínyà láàrin wa.

10) Mo ń gbìyànjú láti má jẹ́ kí ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn bá  àwọn elétò ààbọ̀ látàrí àṣeyọrí tí wọ́n tí ṣe ni ọdún kan àti oṣù díè sẹ́yìn.

11) Wọ́n gbọdọ̀ lé Ìgbé sùnmọ̀mí àti ìwà ọ̀daràn jìnà kí ó le fún gbogbo wa ni àǹfààní láti gbé ní ayọ̀ àti àlàáfíà.

12) Fún ìdí yìí a gbọdọ̀ tún ṣòkòtò wa ṣán làti gbé ogun tí àwọn wọ̀nyí:

Agbé sùmòmí Boko Haram
Àwọn gbọmọgbọmọ, àwọn Darandaran àti àgbẹ̀ àti
Èdè àiyedè láàrin wa pẹ̀lú iranlọwọ àwọn olóṣèlú. A gbọdọ̀ dojú kọ wón.


13) Gbogbo olólùfẹ́ orílè èdè Nàìjíríà, ìsisẹ́ papọ wa yíò jẹ́ kí á le gbé ogun tí àwọn ìpèníjà wọ̀nyí:

·   Ètò ọrọ̀ ajẹ́

·     Ìdàgbàsókè ètò òṣèlú àwa araawa
·       Àti àlàáfíà tó yè kooro láàrin gbogbo ọmọ Nàìjíríà

14) Máa rí wípé gbogbo àwọn ìpèníjà yìí ni a borí wọn. Inú mi dùn láti padà sí orílè-èdè Nàìjíríà.

15) Ẹsẹ́ púpọ̀, Èdùmàrè a tún orílè èdè Nàìjíríà ṣe.

Àmín.

#EdeYorubaRewa

Tuesday, 11 July 2017

Ọ̀RỌ̀ Ìkìlọ̀ 2

Ẹjẹ́ ká gb'áyé ṣe rere,
Ọjọ́ a kú làá dère,
Ènìyàn ò sunwòn láàyè,
Ǹjẹ́ a lè rí ohun gidi sọ nípa rẹ tó bá kú,
Àbí àwọn ènìyàn a máa sọ wípé àtún kú tún kúù rẹ lọrun,
Ẹjẹ́ ká gb'ayé ṣe rere,
Kí ọmọ aráyé lee rí ohun tó dára sọ,
Ẹjẹ́ ká kó pa láti tún, ilé, ọ̀nà, ìlú, orílè èdè wa ṣe,
Kí a kó ipa pàtàkì láwùjo wa,
kí ọmọ aráyé lee sọ nípa wa dára dára tí a bá kú,
Ní tèmi ooo rere lè mi o ṣe,
N ò ní ṣe ìkà,
kí ọmọ aráyé lee sọ ohun gidi nípa mi.

Ìwo ń kọ?

#EdeYorubaRewa

Ọ̀RỌ̀ Ìkìlọ̀

Ohun tá a ṣe ní kọ̀kọ̀
Táa fẹ́ ká ráyè mọ̀ nípa ẹ̀
Ohun tó dára ní,
Èyí táa ṣe ní kọ̀rọ̀
Táà fẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó rí
Ohun burúkú ni
Ṣùgbọ́n bó ò tafà sókè, tó o yídò borí
Bí ọba ayé ò rí ọ, tọ̀run ń wò ọ́
Ìwọ máa gbọ̀nà ẹ̀bùrú
Sọmọ ádámọ lọ́sẹ́
Lójú ilé ni elédùmarè ó gbà mú ọ
Ìwọ tó o ní kú lọ́wọ́
Tó o látaare
Ìwọ tó jẹ́ kìkì ìkà
Tó jẹ́ pẹ́nu to bá kàn ọ o kàn ìjàngbọ̀n
Máa ṣe nìṣó, ẹ̀san ń bọ̀
Rántí pé, ìwà tó o bá hu
Lọmọ máa débá
Ẹni tó gbèbù ìkà ọmọ rẹ yíò je àjeyó ìyà
Yíò je ajẹsẹ́kù dọmọ ọmọ
Ẹ jẹ́ ká gbélé ayé ṣe rere
Ká lè ní gbẹ̀yìn tó dùn.
Kò sí ohun tá a ṣe tí elédùmarè ò rí
Ẹ jẹ ṣe dára ní gbogbo ibikíbi tí a bá wà.



#EdeYorubaRewa

Sunday, 25 June 2017

Àlọ́ Apá kejì

Àyipadà dé fún Ògbójú-ọdẹ ti ó di Ẹlẹ́mu tóó bẹ̀ ti àwọn ará ilú ṣe akiyesi àyipadà yi.  Yorùbá ni “ojú larí, ọ̀rẹ́ ò dénú”. Ìjàpá ọlọ́gbọ́n ẹ̀wẹ́ sọ ara rẹ̀ di ọrẹ kòrí kòsùn pẹ̀lú Ògbójú-ọdẹ nitori àti mọ idi ọrọ̀ rẹ.  Laipẹ, àrùn Ṣọ̀pọ̀ná bo Ògbójú-ọdẹ eleyi dá iṣẹ́ àti gbé ẹmu fún àwọn Ará Ọ̀run dúró.  Gẹgẹbi ọ̀rẹ́ ó bẹ Ìjàpá pé ki ó bá ohun bẹ̀rẹ̀ si gbé ẹmu lọ fún àwọn Ará Ọ̀run.  Ó ṣe ikilọ fún Ìjàpá bi ikilọ ti àwọn Ará Ọ̀run fi silẹ̀.  Ìjàpá, bẹ̀rẹ̀ si gbé ẹmu lọ, ni ọjọ́ keji ti ó ri owó rẹpẹtẹ ti àwọn Ará Ọ̀run kó si idi agbè ẹmu àná, ó pinu lati mọ idi abájọ.

Ìjàpá fi ara pamọ́ si igbó lati wo bi àwọn Ará Ọ̀run ti ńmu ẹmu. Ohun ti ó ri yàá lẹ́nu, ó ri Ori, Ẹsẹ̀, Ojú, Apá àti àwọn ẹ̀yà ara miran ti wọn dá dúró, ti wọn si bẹ̀rẹ̀ si mu ẹmu. Ìjàpá  bẹ̀rẹ̀ si fi àwọn Ará Ọ̀run ṣe yẹ̀yẹ́.  Nigbati wọn gbọ, wọ́n le lati pá ṣùgbọ́n, Ìjàpá sá àsálà fún ẹmi rẹ, ó kó wọ inú ihò, wọn kò ri pa.

Ògbójú-ọdẹ reti titi ki Ìjàpá kó owó ẹmu dé.  Nigbati Ìjàpá dé, ó gbé irọ́ kalẹ̀ pé olè dá ohun lọ́nà, wọn gba gbogbo owó ẹmu lọ ni ohun ṣe pẹ́.

Ara Ògbójú-ọdẹ ya, ó gbé ẹmu lọ fún ara-orun gẹgẹbi iṣe rẹ tẹ́lẹ̀ lai mọ iwà àkóbá ti Ìjàpá ti hù silẹ̀.

Àwọn Ará-Ọ̀run wọ ijàkàdi pẹ̀lú Ògbójú-ọdẹ, nitori ó rú òfin ikilọ ti wọn fun.  Nitori imọ̀ ti ó ni lẹ́nu iṣẹ Ọdẹ, Ará-Ọ̀run ko ri Ògbójú-ọdẹ pa.  Lẹhin ijàkàdi, ó ṣe àlàyé pé ara ohun ni kò yá, ó fi àpá han, pé nitori eyi ni ohun ṣe bẹ ọ̀rẹ́ ohun Ìjàpá ki ó bá ohun gbé ẹmu lọ fún wọn.

Wọn ṣe àlàyé ohun ti Ìjàpá ti ó pè ni ọ̀rẹ́ rẹ ṣe fún wọn.  Ará-Ọ̀run dariji Ògbójú-ọdẹ pẹ̀lú ikilọ pé ki o maṣe gbára lé ọ̀rẹ́. Wọn ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rẹ́ ò ṣé fi okùn ọlà han, nítorí ọ̀pọ̀ ọ̀tá ló ńṣe bi ọ̀rẹ́ nitori àti jẹ.

Ẹsẹ́ púpọ̀ fún ìfojúsọ́nà yín.
#EdeYorubaRewa