Tuesday, 22 August 2017

Ìkéde tí Ààrẹ Muhammad Buhari ṣe

Èyí ni ìkéde tí Ààrẹ Muhammad Buhari ṣe ní ọjọ́ kọkànlélógún, oṣù kẹjọ ọdún 2017 (21/08/2017).

Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà,

1) Mo dúpẹ́ fún Ọlọ́run àti gbogbo ọmọ orílè Nàìjíríà fún àdúrà yín, inú mi dùn láti padà sí orílè èdè Nàìjíríà tí mo tí jẹ Ààrẹ.

2) Dídúró mi ní orílè-èdè United Kingdom, gbogbo ohun tí ó ń lọ ní orílè èdè Nàìjíríà ni mo mọ. Àwọn ọmọ orílè èdè Nàìjíríà gbójú gbóyà láti sọ ohunkóhun, ṣùgbọ́n inú mi bàjé láti gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ mìíràn tí wọ́n ń sọ, pàápàá jù lọ lórí ẹ̀rọ ayélujára.

3) Ní ọdún 2003 lẹ́yìn ìgbátí mọ darapọ̀ mọ òṣèlú, Olóògbé olóyè Emeka Ojukwu wá sí ìlú mi ní Daura gẹ́gẹ́bí àlejò. A sọ̀rọ̀ ni kíkún nípa awon ìpèníjà tí orílè èdè Nàìjíríà ń dójú kọ fún ọjọ́ méjì tí Ilé sii sú báwa níbè. Àwa méjèèjì fi orí ọ̀rọ̀ wa kò wípé orílè èdè Nàìjíríà gbọdọ̀ wà ní Ìsòkan.

4) Ìsòkan orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ti ní ìyanjú kò sì ní ìdúnàdúrà nínú. Àko ní fi ààyè gba àwọn alaimokan láti dá wàhálà àti rògbòdìyàn sílè nítorí bí nkan bá bàjẹ́ tán, ńṣe ni wọn yíò sálọ tí wọn yíò sì jẹ́ kí ẹ̀jẹ̀ alaise ṣòfò.

5) Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó ní aàǹfààní láti gbé ayé àti láti lépa ohun rere tí wọ́n bá fẹ́ ṣe ni ibikíbi ni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láìsí ẹnì kankan tí yíò di wọn lọ́wọ́.


6) Mo nígbàgbọ́ wípé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni ó fi ara mọ́ èróngbà yìí.

 7) Eléyìí kìí ṣe láti di àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti má mọ ohun tí ó kàn wón. Ṣùgbọ́n ẹwà àti ifamora orílẹ̀ èdè gbọdọ̀ fi àyè gba onírúurú ẹgbẹ́ láti ṣisẹ́ kí orílè èdè yìí le tẹsiwaju.

8) Àwọn ilé ìgbìmò Asòfin àti ilé ìgbìmò ní àwọn ìlú kọ̀ọ̀kan ni ẹ̀tọ́ láti  gbìmọ̀ àti láti ṣe ìwádìí tí ó dára.

9) Ìlàkàkà àwọn ọmọ ilẹ̀ ìgbìmò náà ni wípé ó dára kí gbogbo wa máa gbé papọ ni ìrépọ̀ kí ó má sí ìpínyà láàrin wa.

10) Mo ń gbìyànjú láti má jẹ́ kí ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn bá  àwọn elétò ààbọ̀ látàrí àṣeyọrí tí wọ́n tí ṣe ni ọdún kan àti oṣù díè sẹ́yìn.

11) Wọ́n gbọdọ̀ lé Ìgbé sùnmọ̀mí àti ìwà ọ̀daràn jìnà kí ó le fún gbogbo wa ni àǹfààní láti gbé ní ayọ̀ àti àlàáfíà.

12) Fún ìdí yìí a gbọdọ̀ tún ṣòkòtò wa ṣán làti gbé ogun tí àwọn wọ̀nyí:

Agbé sùmòmí Boko Haram
Àwọn gbọmọgbọmọ, àwọn Darandaran àti àgbẹ̀ àti
Èdè àiyedè láàrin wa pẹ̀lú iranlọwọ àwọn olóṣèlú. A gbọdọ̀ dojú kọ wón.


13) Gbogbo olólùfẹ́ orílè èdè Nàìjíríà, ìsisẹ́ papọ wa yíò jẹ́ kí á le gbé ogun tí àwọn ìpèníjà wọ̀nyí:

·   Ètò ọrọ̀ ajẹ́

·     Ìdàgbàsókè ètò òṣèlú àwa araawa
·       Àti àlàáfíà tó yè kooro láàrin gbogbo ọmọ Nàìjíríà

14) Máa rí wípé gbogbo àwọn ìpèníjà yìí ni a borí wọn. Inú mi dùn láti padà sí orílè-èdè Nàìjíríà.

15) Ẹsẹ́ púpọ̀, Èdùmàrè a tún orílè èdè Nàìjíríà ṣe.

Àmín.

#EdeYorubaRewa

Tuesday, 11 July 2017

Ọ̀RỌ̀ Ìkìlọ̀ 2

Ẹjẹ́ ká gb'áyé ṣe rere,
Ọjọ́ a kú làá dère,
Ènìyàn ò sunwòn láàyè,
Ǹjẹ́ a lè rí ohun gidi sọ nípa rẹ tó bá kú,
Àbí àwọn ènìyàn a máa sọ wípé àtún kú tún kúù rẹ lọrun,
Ẹjẹ́ ká gb'ayé ṣe rere,
Kí ọmọ aráyé lee rí ohun tó dára sọ,
Ẹjẹ́ ká kó pa láti tún, ilé, ọ̀nà, ìlú, orílè èdè wa ṣe,
Kí a kó ipa pàtàkì láwùjo wa,
kí ọmọ aráyé lee sọ nípa wa dára dára tí a bá kú,
Ní tèmi ooo rere lè mi o ṣe,
N ò ní ṣe ìkà,
kí ọmọ aráyé lee sọ ohun gidi nípa mi.

Ìwo ń kọ?

#EdeYorubaRewa

Ọ̀RỌ̀ Ìkìlọ̀

Ohun tá a ṣe ní kọ̀kọ̀
Táa fẹ́ ká ráyè mọ̀ nípa ẹ̀
Ohun tó dára ní,
Èyí táa ṣe ní kọ̀rọ̀
Táà fẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó rí
Ohun burúkú ni
Ṣùgbọ́n bó ò tafà sókè, tó o yídò borí
Bí ọba ayé ò rí ọ, tọ̀run ń wò ọ́
Ìwọ máa gbọ̀nà ẹ̀bùrú
Sọmọ ádámọ lọ́sẹ́
Lójú ilé ni elédùmarè ó gbà mú ọ
Ìwọ tó o ní kú lọ́wọ́
Tó o látaare
Ìwọ tó jẹ́ kìkì ìkà
Tó jẹ́ pẹ́nu to bá kàn ọ o kàn ìjàngbọ̀n
Máa ṣe nìṣó, ẹ̀san ń bọ̀
Rántí pé, ìwà tó o bá hu
Lọmọ máa débá
Ẹni tó gbèbù ìkà ọmọ rẹ yíò je àjeyó ìyà
Yíò je ajẹsẹ́kù dọmọ ọmọ
Ẹ jẹ́ ká gbélé ayé ṣe rere
Ká lè ní gbẹ̀yìn tó dùn.
Kò sí ohun tá a ṣe tí elédùmarè ò rí
Ẹ jẹ ṣe dára ní gbogbo ibikíbi tí a bá wà.



#EdeYorubaRewa

Sunday, 25 June 2017

Àlọ́ Apá kejì

Àyipadà dé fún Ògbójú-ọdẹ ti ó di Ẹlẹ́mu tóó bẹ̀ ti àwọn ará ilú ṣe akiyesi àyipadà yi.  Yorùbá ni “ojú larí, ọ̀rẹ́ ò dénú”. Ìjàpá ọlọ́gbọ́n ẹ̀wẹ́ sọ ara rẹ̀ di ọrẹ kòrí kòsùn pẹ̀lú Ògbójú-ọdẹ nitori àti mọ idi ọrọ̀ rẹ.  Laipẹ, àrùn Ṣọ̀pọ̀ná bo Ògbójú-ọdẹ eleyi dá iṣẹ́ àti gbé ẹmu fún àwọn Ará Ọ̀run dúró.  Gẹgẹbi ọ̀rẹ́ ó bẹ Ìjàpá pé ki ó bá ohun bẹ̀rẹ̀ si gbé ẹmu lọ fún àwọn Ará Ọ̀run.  Ó ṣe ikilọ fún Ìjàpá bi ikilọ ti àwọn Ará Ọ̀run fi silẹ̀.  Ìjàpá, bẹ̀rẹ̀ si gbé ẹmu lọ, ni ọjọ́ keji ti ó ri owó rẹpẹtẹ ti àwọn Ará Ọ̀run kó si idi agbè ẹmu àná, ó pinu lati mọ idi abájọ.

Ìjàpá fi ara pamọ́ si igbó lati wo bi àwọn Ará Ọ̀run ti ńmu ẹmu. Ohun ti ó ri yàá lẹ́nu, ó ri Ori, Ẹsẹ̀, Ojú, Apá àti àwọn ẹ̀yà ara miran ti wọn dá dúró, ti wọn si bẹ̀rẹ̀ si mu ẹmu. Ìjàpá  bẹ̀rẹ̀ si fi àwọn Ará Ọ̀run ṣe yẹ̀yẹ́.  Nigbati wọn gbọ, wọ́n le lati pá ṣùgbọ́n, Ìjàpá sá àsálà fún ẹmi rẹ, ó kó wọ inú ihò, wọn kò ri pa.

Ògbójú-ọdẹ reti titi ki Ìjàpá kó owó ẹmu dé.  Nigbati Ìjàpá dé, ó gbé irọ́ kalẹ̀ pé olè dá ohun lọ́nà, wọn gba gbogbo owó ẹmu lọ ni ohun ṣe pẹ́.

Ara Ògbójú-ọdẹ ya, ó gbé ẹmu lọ fún ara-orun gẹgẹbi iṣe rẹ tẹ́lẹ̀ lai mọ iwà àkóbá ti Ìjàpá ti hù silẹ̀.

Àwọn Ará-Ọ̀run wọ ijàkàdi pẹ̀lú Ògbójú-ọdẹ, nitori ó rú òfin ikilọ ti wọn fun.  Nitori imọ̀ ti ó ni lẹ́nu iṣẹ Ọdẹ, Ará-Ọ̀run ko ri Ògbójú-ọdẹ pa.  Lẹhin ijàkàdi, ó ṣe àlàyé pé ara ohun ni kò yá, ó fi àpá han, pé nitori eyi ni ohun ṣe bẹ ọ̀rẹ́ ohun Ìjàpá ki ó bá ohun gbé ẹmu lọ fún wọn.

Wọn ṣe àlàyé ohun ti Ìjàpá ti ó pè ni ọ̀rẹ́ rẹ ṣe fún wọn.  Ará-Ọ̀run dariji Ògbójú-ọdẹ pẹ̀lú ikilọ pé ki o maṣe gbára lé ọ̀rẹ́. Wọn ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rẹ́ ò ṣé fi okùn ọlà han, nítorí ọ̀pọ̀ ọ̀tá ló ńṣe bi ọ̀rẹ́ nitori àti jẹ.

Ẹsẹ́ púpọ̀ fún ìfojúsọ́nà yín.
#EdeYorubaRewa


Àlọ́ Apá kinni

Ọkunrin kan wa láyé àtijọ́, Ògbójú-ọdẹ ni, ṣùgbọ́n bi ó ti pa ẹran tó, kò fi dá nkan ṣe.  Ọ̀pọ̀ igbà, ki ri ẹran ti ó bá pa tà, o ma ńpin fún ará ilú ni.  Nigbati kò ri ẹran pa mọ́, ó di Ọdẹ-apẹyẹ.

Ni ọjọ kan, ògbójú-ọde yi ri ẹyẹ Òfú kan, ṣùgbọ́n ọta ibọn kan ṣoṣo ló kù ninú ibọn rẹ.  Gẹgẹbi Ògbójú-ọdẹ, o yin ẹyẹ Òfú ni ibọn, ọta kan ṣoṣo yi si báa.  Ó bá wọ igbó lọ lati gbé ẹyẹ ti ó pa, lai mọ̀ pé ẹyẹ yi kò kú.  Ó ṣe akitiyan lati ri ẹyẹ́ yi mu, kẹ̀rẹ̀kẹ̀rẹ̀ ó bẹ̀rẹ̀ si wọ igbó lọ titi tó fi ṣi ọ̀nà dé ilẹ̀ àwọn Ará Ọ̀run àwọn ti wọn ńpè ni Abàmi-ẹ̀dá.

Inu bi àwọn Ará Ọ̀run nitori Ògbójú-ọdẹ yi jálu ipàdé wọn.  Wọn gbamú, wọn ni ki ó ṣe àlàyé bi ó ṣe dé ilẹ̀ wọn ki àwọn tó pá.  Ọdẹ ṣe àlàyé ohun ti ojú rẹ ti ri nipa iṣẹ́ àti jẹ àti gbogbo ohun ti ojú rẹ ti ri lẹ́nu iṣẹ́ ọdẹ.  Àwọn Ará-Ọ̀run ṣe àánú rẹ, wọn bèrè pé ṣe ó lè dá ẹmu, ó ni ohun lè dá ẹmu diẹ-diẹ.  Wọn gbaa ni iyànjú pé ki o maṣe fi ojú di iṣẹ kankan, nitori naa, ki ó bẹ̀rẹ̀ si dá ẹmu fún àwọn.

Wọn ṣe ikilọ pe, bi ó bá ti gbé ẹmu wá, kò gbọdọ̀ wo bi àwọn ti ńmu ẹmu, ki ó kàn gbé ẹmu silẹ ki o si yi padà lai wo ẹ̀hin.  Bi ó bá rú òfin yi, àwọn yio pa.  Ọdẹ bẹ̀rẹ̀ si gbé ẹmu lọ fún ara orun.  Bi ó bá gbé ẹmu dé, a bẹ̀rẹ̀ si kọrin báyìí:

Ará Ọ̀run, Ará Ọ̀run------------ Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Ará Ọ̀run, Ará Ọ̀run o,---------- Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Ki lo wá ṣe n’ilẹ̀ yi o-------------- Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Ẹmu ni mo wá dá,----------------- Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Èlèló lẹmu rẹ------------------Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Ọ̀kànkàn ẹgbẹ̀wá,-----------------Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Gbẹ́mu silẹ ko maa lọ------------Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbà

Ará Ọ̀run, Ará Ọ̀run o,----------------Ìnọ̀mbà téré, tere múdè, ìnọ̀mbàaa

Lẹ́yìn èyi á gbé ẹmu silẹ á yi padà lai wo ẹ̀hin gẹgẹ bi ikilọ Ará Ọ̀run. Ni ọjọ́ keji, á bá owó ni idi agbè ti ó fi gbé ẹmu tàná wá.
Ẹ kú ojú lọ́nà fún ìyókù.

#EdeYorubaRewa


Monday, 29 May 2017

Ayẹyẹ ìjọba tiwantiwa

Ó pé ọdún kejìdínlógún tí orílè èdè Nàìjíríà tí ń lo ìjọba tiwantiwa leyin igba ti ológun tí ń darí wá.

Mo kí gbogbo àwọn ọmọ orílè èdè Nàìjíríà nílé lóko àti lẹ́yìn odi wípé a kú ayẹyẹ ìjọba tiwantiwa (Happy Democracy day). Mo mọ wípé inú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ni o dùn látàrí bí nkan ṣe rí, ẹ jẹ́ kí a nígbàgbọ́ ni àwọn tí ó wà lórí ipò báyìí wípé wọn a mú wa dé èbúté ògo.

"Ọ̀rọ̀ Yorùbá kan ló sọ wípé sùúrù kìí pọ̀ jù àfi tí kò bá ní tó."
Mo mọ wípé ìjọba tí a ní lori ipò báyìí ń gbìyànjú láti jẹ́ kí orílè èdè Nàìjíríà dara,ki o rọrùn fún tolórí telémù,Ǹkan tí ó ti bá jẹ́ fún ọdún mẹ́tadínlógún kólé ṣe ẹ túnṣe láàrin ọdún díè tí àwọn ìjọba yìí dé ibè ìdí nì tí ó fi ye ká ní sùúrù.
Ìjọba  Nàìjíríà,  ẹ bá wà tún orílè èdè wa ṣe, ẹsẹ àtúnṣe sì gbogbo ohun tí oti bàjé kí inú àwọn tí ó dibo fún yín lé dùn.

Iṣẹ́ wa lọ́wọ́ àwa náà tí a jẹ́ ọmọ orílè èdè Nàìjíríà, lábé bí ó ti wù kí ó rí Ẹjẹ́ kí àwa náà rán ìjọba lọ́wọ́ látàrí kí a jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn rere

Gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà ẹ jẹ ká ní sùúrù àti èmi ìfaradà fún Ààrẹ Muhammad Buhari àti gbogbo àwọn tí ó kó sódì kí wọn lè mú wa dé èbúté ògo.

Dídára orílè èdè Nàìjíríà ó wà lọ́wọ́ èmi àti ìwọ ẹ jẹ́ kí á jọ ṣe.orílẹ̀ èdè Nàìjíríà yíò dára tí ó bá dára tán kí wọn má fi wa ṣe àwátì

🇳🇬🇳🇬🇳🇬🇳🇬🇳🇬
Semiat Olufunke Tiamiyu
#EdeYorubaRewa



Thursday, 25 May 2017

Ìtàn òwe Yorùbá

Ìtàn tí ó rò mó òwe Yorùbá yìí,

                   "Kí lo rí l'ọ́bẹ̀ tí fi waaro ọwọ́."

Ní bí ọdún díè sẹ́yìn, ìlú kan wà tí wọ́n ń pè ní Kuo, ó wá ní Bode Saadu ni Ìpínlẹ̀ Kwara ṣùgbọ́n ìlú tí à ń sọ yìí jóná ni ọdún 1814.

Gbogbo Yorùbá kó ló máa ń lo òwe yìí tẹ́lẹ̀, ogun ni ó sì fà á tí òwe yìí fi wáyé.
Ìlú tí a ń pè ní Kuo yìí ni olórí tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Sholá Gberú. Nígbà tí ìlú Kuo jóná Sholá Gberú kò gbogbo àwọn ọmọ, ẹrú àti gbogbo ohun tí wọ́n ni lọ sí ìlú Ilorin,nígbà náà afonja wa láyé. Ìlú kan wà láàrin Ọ̀yọ́ àti Ilorin,ìlú Gbógun ni ìlú náà ń jẹ́, tí ogún bá sì fẹ́ ja Ọ̀yọ́ wọn gbodo kọ́kọ́ ja ìlú Gbógun tí à ń Wiyi. Nígbà tí wọ́n fẹ́ kogun ja ìlú Gbógun ALÁNÀMÚ ni lèdí àpò pọ̀  láti kogun ja ìlú Gbógun.


Arákùnrin tí wọ́n ń pè Alánàmú Pankere ní o ma ń fi jà, tí ó bá ti fi náà ẹni tí wọ́n dìjọ ń jà fi ń jà, ẹni náà ara rẹ̀ yíò wálè yíò sì na'wọ́ mú ẹni náà ìdí rẹ tí wọ́n fi ń pe ni ALÁNÀMÚ.
Alánàmú sì so ọwọ́ pò mo Ilorin, wọn sì mú orí ìyàwó ọ̀pẹ̀lẹ̀ mó ara, Wọ́n fún ní májẹ̀lé pé kí ó fi si inú oúnjẹ. Wọ́n rán àgbà ọmọ Sholá Gberú sí ọ̀pẹ̀lẹ̀, ìyàwó ọ̀pẹ̀lẹ̀ dáná oúnjẹ, ó sì ti fi májẹ̀lé si inú ounje náà, ọ̀pẹ̀lẹ̀ àti ọmọ Sholá Gberú tí fọ ọwọ́, bí ọmọ Sholá Gberú tí bu òkèlè pé kí ohun fi kan ọbẹ̀
Ó bá wararo ọwọ́. Ọ̀pẹ̀lẹ̀ bíi pé kí lórí l'ọ́bẹ̀ tí ó fi wararo ọwọ́, ló bá ní májẹ̀lé rẹ nínú ọbẹ̀.....
Báyìí ni Ọ̀pẹ̀lẹ̀ ni Bí kú ilé ọ bá pani tode ó lè pani.

Ìtàn tí ó rò mó òwe KÍ LO RÍ L'Ọ́BẸ̀ TÍ Ó FI WAARO ỌWỌ́. májẹ̀lé ni ó rí l'ọ́bẹ̀ tí ó fi Wararo ọwọ́.

Mo lérò wípé ẹ gbádùn ìtàn yìí.

#EdeYorubaRewa